Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹnẹsisi 17:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Nígbà tí Abramu di ẹni ọdún mọkandinlọgọrun-un, OLUWA farahàn án, ó sọ fún un pé, “Èmi ni Ọlọrun Olodumare, máa gbọ́ tèmi, kí o sì jẹ́ pípé.

2. N óo bá ọ dá majẹmu kan, tí yóo wà láàrin èmi pẹlu rẹ, n óo sì bukun ọ lọpọlọpọ.”

3. Abramu bá dojúbolẹ̀, Ọlọrun tún wí fún un pé,

4. “Majẹmu tí mo bá ọ dá kò yẹ̀ rárá: O óo jẹ́ baba ńlá fún ọpọlọpọ orílẹ̀ èdè.

Ka pipe ipin Jẹnẹsisi 17