Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 7:4-15 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Sọ fún ọgbọ́n pé, “Ìwọ ni arabinrin mi,”kí o sì pe ìmọ̀ ní ọ̀rẹ́ kòríkòsùn rẹ,

5. kí wọ́n baà lè pa ọ́ mọ́,kúrò lọ́dọ̀ alágbèrè obinrin,ati kúrò lọ́wọ́ onírìnkurìn pẹlu ọ̀rọ̀ dídùn rẹ̀.

6. Mo yọjú wo ìta,láti ojú fèrèsé ilé mi.

7. Mo rí àwọn ọ̀dọ́ tí wọn kò ní ìrírí,mo ṣe akiyesi pé láàrin wọn,ọmọkunrin kan wà tí kò gbọ́n.

8. Ó ń lọ ní òpópónà, lẹ́bàá kọ̀rọ̀ ilé alágbèrè obinrin náà,

9. ní àṣáálẹ́, nígbà tí ọjọ́ ń pofírí,tí ilẹ̀ ti ń ṣú, tí òkùnkùn ti ń kùn.

10. Obinrin kan lọ pàdé rẹ̀,ó wọ aṣọ aṣẹ́wó,ọkàn rẹ̀ kún fún ẹ̀tàn.

11. Ó jẹ́ aláriwo ati onírìnkurìn obinrin,kì í gbélé rẹ̀.

12. Bí ó ti ń rìn kiri lójú pópó,bẹ́ẹ̀ ni yóo máa lọ, tí yóo máa bọ̀ láàrin ọjà,yóo máa dọdẹ kiri ní gbogbo kọ̀rọ̀.

13. Yóo bá dì mọ́ ọmọkunrin tí kò gbọ́n náà, yóo fi ẹnu kò ó lẹ́nu,yóo wí pẹlu ainitiju pé,

14. “Mo ti rú ẹbọ alaafia,mo sì ti san ẹ̀jẹ́ mi lónìí.

15. Nítorí náà, mo wá pàdé rẹ,mo fi ìlara wá ọ, mo sì rí ọ.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 7