Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 6:8-27 BIBELI MIMỌ (BM)

8. sibẹsibẹ, a máa tọ́jú oúnjẹ rẹ̀ ní àkókò ẹ̀ẹ̀rùn;a sì máa kó oúnjẹ jọ, ní àkókò ìkórè.

9. O óo ti sùn pẹ́ tó, ìwọ ọ̀lẹ?Ìgbà wo ni o óo tají lójú oorun?

10. Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀,ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi,

11. yóo jẹ́ kí òṣì dé bá ọ, bí ọlọ́ṣà dé bá eniyan. Àìní yóo sì dé bá ọ bíi jagunjagun dé báni.

12. Eniyan lásán, ìkà eniyan, a máa rìn káàkiri,a máa sọ̀rọ̀ àrékérekè,

13. bí ó ti ń ṣẹ́jú, bẹ́ẹ̀ ni ó ń jansẹ̀ mọ́lẹ̀,tí ó sì ń fi ìka ṣe àpèjúwe.

14. Ó ń fi inú burúkú pète ibi, ó sì ń fi ojoojumọ dá ìjà sílẹ̀,

15. nítorí náà, ibi yóo dé bá a lójijì,yóo parun kíá láìsí àtúnṣe.

16. Àwọn nǹkan mẹfa kan wà tí OLUWA kò fẹ́:wọ́n tilẹ̀ tó meje tí ó jẹ́ ohun ìríra fún un:

17. Ìgbéraga, irọ́ pípa,ẹni tí ń déédé pa aláìṣẹ̀,

18. ọkàn tí ń pète ìkà,ẹsẹ̀ tí ń sáré sí ibi,

19. ẹlẹ́rìí èké tí ẹnu rẹ̀ kún fún irọ́,ati ẹni tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrin eniyan.

20. Ọmọ mi, pa òfin baba rẹ mọ́,má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.

21. Fi wọ́n sọ́kàn nígbà gbogbo,kí o sì so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ.

22. Nígbà tí o bá ń lọ, wọn yóo máa tọ́ ọ,bí o bá sùn, wọn yóo máa ṣọ́ ọ,bí o bá jí, wọn yóo máa bá ọ sọ̀rọ̀.

23. Nítorí fìtílà ni òfin,ìmọ́lẹ̀ ni ẹ̀kọ́, ìbáwí sì jẹ́ ọ̀nà ìyè,

24. láti pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ obinrin burúkú,ati lọ́wọ́ ẹnu alágbèrè obinrin tí ó dùn lọ́rọ̀.

25. Má jẹ́ kí ẹwà rẹ̀ wù ọ́,má sì ṣe jẹ́ kí ó fi ìpéǹpéjú rẹ̀ mú ọ.

26. Owó tí aṣẹ́wó yóo gbà kò ju owó burẹdi lọ,ṣugbọn gbogbo ẹ̀mí rẹ ni alágbèrè yóo fi ọgbọ́n gbà.

27. Ǹjẹ́ ẹnìkan lè gbé iná ka àyà,kí aṣọ rẹ̀ má jó?

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 6