Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 6:7-21 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Ẹ̀dá tí kò ní olórí, tabi alabojuto, tabi aláṣẹ

8. sibẹsibẹ, a máa tọ́jú oúnjẹ rẹ̀ ní àkókò ẹ̀ẹ̀rùn;a sì máa kó oúnjẹ jọ, ní àkókò ìkórè.

9. O óo ti sùn pẹ́ tó, ìwọ ọ̀lẹ?Ìgbà wo ni o óo tají lójú oorun?

10. Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀,ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi,

11. yóo jẹ́ kí òṣì dé bá ọ, bí ọlọ́ṣà dé bá eniyan. Àìní yóo sì dé bá ọ bíi jagunjagun dé báni.

12. Eniyan lásán, ìkà eniyan, a máa rìn káàkiri,a máa sọ̀rọ̀ àrékérekè,

13. bí ó ti ń ṣẹ́jú, bẹ́ẹ̀ ni ó ń jansẹ̀ mọ́lẹ̀,tí ó sì ń fi ìka ṣe àpèjúwe.

14. Ó ń fi inú burúkú pète ibi, ó sì ń fi ojoojumọ dá ìjà sílẹ̀,

15. nítorí náà, ibi yóo dé bá a lójijì,yóo parun kíá láìsí àtúnṣe.

16. Àwọn nǹkan mẹfa kan wà tí OLUWA kò fẹ́:wọ́n tilẹ̀ tó meje tí ó jẹ́ ohun ìríra fún un:

17. Ìgbéraga, irọ́ pípa,ẹni tí ń déédé pa aláìṣẹ̀,

18. ọkàn tí ń pète ìkà,ẹsẹ̀ tí ń sáré sí ibi,

19. ẹlẹ́rìí èké tí ẹnu rẹ̀ kún fún irọ́,ati ẹni tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrin eniyan.

20. Ọmọ mi, pa òfin baba rẹ mọ́,má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.

21. Fi wọ́n sọ́kàn nígbà gbogbo,kí o sì so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 6