Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 5:3-16 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Nítorí ẹnu alágbèrè obinrin a máa dùn bí oyin,ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì tuni lára ju òróró lọ,

4. ṣugbọn níkẹyìn ọ̀rọ̀ rẹ̀ á korò bí iwọ,ẹnu rẹ̀ á sì mú bí idà olójú meji.

5. Ẹsẹ̀ rẹ̀ ń dà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ lọ sinu ikú,ìgbésẹ̀ rẹ̀ sì lọ tààrà sinu ibojì.

6. Ó kọ̀ láti rin ọ̀nà ìyè,ọ̀nà rẹ̀ wọ́, kò sì mọ̀.

7. Nisinsinyii, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,ẹ má sì kọ ọ̀rọ̀ sí mi lẹ́nu.

8. Ẹ jìnnà sí alágbèrè obinrin,kí ẹ má tilẹ̀ súnmọ́ ẹnu ọ̀nà rẹ̀,

9. kí ẹ má baà gbé ògo yín fún ẹlòmíràn,kí ẹ sì fi ìgbé ayé yín lé aláìláàánú lọ́wọ́.

10. Kí àjèjì má baà jèrè iṣẹ́ yín,kí làálàá rẹ má sì bọ́ sápò àlejò.

11. Kí o má baà kérora nígbẹ̀yìn ayé rẹ,nígbà tí o bá di ìjẹ fún ẹni ẹlẹ́ni

12. nígbà náà ni o óo wí pé,“Kí ló dé tí mo kórìíra ìtọ́ni,tí ọkàn mi sì kẹ́gàn ìbáwí!

13. N kò fetí sí ọ̀rọ̀ àwọn olùkọ́ min kò sì gba ti àwọn tí wọn ń tọ́ mi sọ́nà.

14. Èyí ni ó sún mi dé etí bèbè ìparun,láàrin àwùjọ eniyan.”

15. Ìwọ ọkọ, láti inú àmù rẹ ni kí o ti máa mu omi;omi tí ń sun láti inú kànga rẹ ni kí o máa mu.

16. Kò dára kí orísun rẹ máa ṣàn káàkiri,bí omi àgbàrá ní gbogbo òpópónà.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 5