Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 4:9-17 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Yóo fi nǹkan ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà bò ọ́ lórí,yóo sì dé ọ ní adé dáradára.”

10. Gbọ́, ọmọ mi, gba ẹ̀kọ́ mi,kí ẹ̀mí rẹ lè gùn.

11. Mo ti kọ́ ọ ní ọgbọ́n,mo sì ti fẹsẹ̀ rẹ lé ọ̀nà òtítọ́.

12. Nígbà tí o bá ń rìn, o kò ní rí ìdínà,nígbà tí o bá ń sáré, o kò ní fi ẹsẹ̀ kọ.

13. Di ẹ̀kọ́ mú ṣinṣin,má jẹ́ kí ó bọ́,pa á mọ́, nítorí òun ni ìyè rẹ.

14. Má ṣe gba ọ̀nà ẹni ibi,má sì ṣe rin ọ̀nà eniyan burúkú.

15. Yẹra fún un,má tilẹ̀ kọjú sí ọ̀nà ibẹ̀,ṣugbọn gba ibòmíràn, kí o máa bá tìrẹ lọ.

16. Nítorí wọn kì í lè é sùn, bí wọn kò bá tíì ṣe ibi,oorun kì í kùn wọ́n, tí wọn kò bá tíì fa ìṣubú eniyan.

17. Ìkà ṣíṣe ni oúnjẹ wọn,ìwà ipá sì ni ọtí waini wọn.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 4