Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 4:8-20 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Gbé ọgbọ́n lárugẹ, yóo sì gbé ọ ga,yóo bu ọlá fún ọ, bí o bá gbà á mọ́ra.

9. Yóo fi nǹkan ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà bò ọ́ lórí,yóo sì dé ọ ní adé dáradára.”

10. Gbọ́, ọmọ mi, gba ẹ̀kọ́ mi,kí ẹ̀mí rẹ lè gùn.

11. Mo ti kọ́ ọ ní ọgbọ́n,mo sì ti fẹsẹ̀ rẹ lé ọ̀nà òtítọ́.

12. Nígbà tí o bá ń rìn, o kò ní rí ìdínà,nígbà tí o bá ń sáré, o kò ní fi ẹsẹ̀ kọ.

13. Di ẹ̀kọ́ mú ṣinṣin,má jẹ́ kí ó bọ́,pa á mọ́, nítorí òun ni ìyè rẹ.

14. Má ṣe gba ọ̀nà ẹni ibi,má sì ṣe rin ọ̀nà eniyan burúkú.

15. Yẹra fún un,má tilẹ̀ kọjú sí ọ̀nà ibẹ̀,ṣugbọn gba ibòmíràn, kí o máa bá tìrẹ lọ.

16. Nítorí wọn kì í lè é sùn, bí wọn kò bá tíì ṣe ibi,oorun kì í kùn wọ́n, tí wọn kò bá tíì fa ìṣubú eniyan.

17. Ìkà ṣíṣe ni oúnjẹ wọn,ìwà ipá sì ni ọtí waini wọn.

18. Ṣugbọn ọ̀nà olódodo dàbí ìmọ́lẹ̀ àfẹ̀mọ́júmọ́,tí ń mọ́lẹ̀ sí i láti ìdájí títí tí ilẹ̀ yóo fi mọ́ kedere.

19. Ọ̀nà eniyan burúkú dàbí òkùnkùn biribiri,wọn kò mọ ohun tí wọn yóo dìgbò lù.

20. Ọmọ mi, fetí sí ọ̀rọ̀ mi,tẹ́tí sílẹ̀ sí ohun tí mò ń sọ.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 4