Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 3:23-30 BIBELI MIMỌ (BM)

23. Nígbà náà ni o óo máa rìnláìléwu ati láìkọsẹ̀.

24. Bí o bá jókòó, ẹ̀rù kò ní bà ọ́,bí o bá sùn, oorun yóo máa dùn mọ́ ọ.

25. Má bẹ̀rù àjálù òjijì,tabi ìparun àwọn ẹni ibi,nígbà tí ó bá dé bá ọ,

26. nítorí pé, OLUWA ni igbẹkẹle rẹ,kò sì ní jẹ́ kí o ti ẹsẹ̀ bọ tàkúté.

27. Má ṣe fa ọwọ́ ire sẹ́yìn lọ́dọ̀ àwọn tí ó tọ́ sí, nígbà tí ó bá wà ní ìkáwọ́ rẹ láti ṣe é.

28. Má sọ fún aládùúgbò rẹ pé,“Máa lọ ná, n óo fún ọ tí o bá pada wá lọ́la,”nígbà tí ohun tí ó fẹ́ wà lọ́dọ̀ rẹ.

29. Má ṣe gbèrò ibi sí aládùúgbò rẹtí ń fi inú kan bá ọ gbé.

30. Má ṣe bá ẹnikẹ́ni jà láìnídìí,nígbà tí kò ṣe ọ́ níbi.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 3