Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 3:10-22 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Nígbà náà ni àká rẹ yóo kún bámúbámú,ìkòkò waini rẹ yóo sì kún àkúnya.

11. Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìtọ́ni OLUWA, má sì ṣe jẹ́ kí ìbáwí rẹ̀ sú ọ.

12. Nítorí ẹni tí OLUWA bá fẹ́ níí báwí gẹ́gẹ́ bí baba tí máa ń bá ọmọ rẹ̀ tí ó bá fẹ́ràn wí.

13. Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó wá ọgbọ́n rí,ati ẹni tí ó ní òye.

14. Nítorí èrè rẹ̀ dáraju èrè orí fadaka ati ti wúrà lọ.

15. Ọgbọ́n níye lóríó ju ohun ọ̀ṣọ́ olówó iyebíye lọ,kò sí ohun tí o lè fi wé e,ninu gbogbo ohun tí ọkàn rẹ lè fẹ́.

16. Ẹ̀mí gígùn wà ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀,ọrọ̀ ati iyì sì wà ní ọwọ́ òsì rẹ̀.

17. Ọ̀nà rẹ̀ tura pupọ,alaafia sì ni gbogbo ọ̀nà rẹ̀.

18. Igi ìyè ni fún àwọn tí wọ́n rọ̀ mọ́ ọn,ayọ̀ sì ń bẹ fún àwọn tí wọ́n dì í mú ṣinṣin.

19. Ọgbọ́n ni OLUWA fi fi ìdí ayé sọlẹ̀,òye ni ó sì fi dá ọ̀run.

20. Nípa ìmọ̀ rẹ̀ ni ibú fi ń tú omi jáde,tí ìrì fi ń sẹ̀ láti inú ìkùukùu.

21. Ọmọ mi, di ọgbọ́n tí ó yè kooro ati làákàyè mú,má sì ṣe jẹ́ kí wọn bọ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ,

22. wọ́n yóo jẹ́ ìyè fún ẹ̀mí rẹ,ati ohun ọ̀ṣọ́ ní ọrùn rẹ.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 3