Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 29:14-20 BIBELI MIMỌ (BM)

14. Ọba tí ó dájọ́ ẹ̀tọ́ fún talaka,ní a óo fìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ títí.

15. Pàṣán ati ìbáwí a máa kọ́ ọmọ lọ́gbọ́n,ọmọ tí a bá fi sílẹ̀ yóo dójúti ìyá rẹ̀.

16. Nígbà tí eniyan burúkú bá wà lórí oyè, ẹ̀ṣẹ̀ a máa pọ̀ síi,ṣugbọn lójú olódodo ni wọn yóo ti ṣubú.

17. Tọ́ ọmọ rẹ, yóo sì fún ọ ní ìsinmi,yóo sì mú inú rẹ dùn.

18. Orílẹ̀-èdè tí kò bá ní ìfihàn láti ọ̀run, yóo dàrú,ṣugbọn ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ń pa òfin mọ́.

19. Ọ̀rọ̀ ẹnu nìkan kò tó láti fi bá ẹrú wí,ó lè fi etí gbọ́ ṣugbọn kí ó má ṣe ohunkohun.

20. Òmùgọ̀ nírètí ju ẹni tí yóo sọ̀rọ̀ sọ̀rọ̀,tí kò lè kó ara rẹ̀ ní ìjánu lọ.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 29