Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 27:12-27 BIBELI MIMỌ (BM)

12. Amòye eniyan rí ewu, ó sì fi ara rẹ̀ pamọ́,ṣugbọn òpè kọjá lọ láàrin rẹ̀, ó sì jìyà rẹ̀.

13. Gba ẹ̀wù ẹni tí ó bá ṣe onídùúró fún àlejò,kí o sì gba nǹkan ìdógò lọ́wọ́ rẹ̀,tí ó bá ṣe onídùúró fún àjèjì obinrin.

14. Ẹni tí ó jí ní kutukutu òwúrọ̀,tí ó ń fi ariwo kí aládùúgbò rẹ̀,kò yàtọ̀ sí ẹni tí ń ṣépè.

15. Iyawo oníjà dàbí omi òjò,tí ń kán tó! Tó! Tó! Láì dáwọ́ dúró;

16. ẹni tí bá ń gbìyànjú láti dá irú obinrin bẹ́ẹ̀ lẹ́kundàbí ẹni tí ń gbìyànjú láti dá afẹ́fẹ́ dúró,tabi ẹni tó fẹ́ fi ọwọ́ mú epo.

17. Bí irin ti ń pọ́n irin,bẹ́ẹ̀ ni eniyan ń kẹ́kọ̀ọ́ lára ẹnìkejì rẹ̀.

18. Ẹni tí ń tọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ yóo rí èso rẹ̀ jẹ,ẹni tí ń tọ́jú ọ̀gá rẹ̀ yóo gba ìyìn rẹ̀.

19. Bí omi tíí fi bí ojú ẹni ti rí han ni,bẹ́ẹ̀ ni ọkàn eniyan ń fi irú ẹni tí eniyan jẹ́ hàn.

20. Ìparun ati isà òkú kò lè ní ìtẹ́lọ́rùn,bẹ́ẹ̀ náà ni ojú eniyan, kì í ní ìtẹ́lọ́rùn.

21. Iná ni a fi ń dán wúrà ati fadaka wò,ìyìn ni a fi ń dán eniyan wò.

22. Wọn ì báà ju òmùgọ̀ sinu odó,kí wọn fi ọmọ odó gún un pọ̀ mọ́ ọkà,ẹnìkan kò lè gba ìwà òmùgọ̀ lọ́wọ́ rẹ̀.

23. Rí i dájú pé o mọ̀ bí agbo ẹran rẹ ti rí,sì máa tọ́jú ọ̀wọ́ ẹran rẹ dáradára;

24. nítorí ọrọ̀ kì í pẹ́ lọ títí,kí adé pẹ́ lórí kì í ṣe láti ìrandíran.

25. Lẹ́yìn tí a bá gé koríko, tí koríko tútù mìíràn sì hù,tí a bá kó koríko tí a gé lára àwọn òkè wálé,

26. o óo rí irun aguntan fi hun aṣọ,o óo sì lè fi owó tí o bá pa lórí àwọn ewúrẹ́ rẹ ra ilẹ̀.

27. O óo rí omi wàrà ewúrẹ́ rẹ fún, tí o óo máa rí mu,ìwọ ati ìdílé rẹ, ati àwọn iranṣẹbinrin rẹ pẹlu.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 27