Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 26:7-18 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Bí ẹsẹ̀ arọ, tí kò wúlò,ni òwe rí lẹ́nu òmùgọ̀.

8. Bí ẹni fi òkúta sinu kànnàkànnà,ni ẹni tí ń yẹ́ òmùgọ̀ sí rí.

9. Bí ẹ̀gún tí ó gún ọ̀mùtí lọ́wọ́,ni òwe rí lẹ́nu òmùgọ̀.

10. Ẹni tí ó gba òmùgọ̀ tabi ọ̀mùtí sí iṣẹ́dàbí tafàtafà tí ń pa eniyan lára kiri.

11. Bí ajá tíí pada sídìí èébì rẹ̀bẹ́ẹ̀ ni òmùgọ̀ tó pada sí ìwà agọ̀ rẹ̀.

12. Ìrètí ń bẹ fún òmùgọ̀ju ẹni tí ó gbọ́n lójú ara rẹ̀ lọ.

13. Ọ̀lẹ ń wí pé, “Kinniun kan wà lọ́nà!Kinniun buburu kan wà ní ìgboro!”

14. Bí ìlẹ̀kùn ṣe ń ṣí síhìn-ín, sọ́hùn-ún, lórí ìdè rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ ń yí síhìn-ín, sọ́hùn-ún, lórí ibùsùn rẹ̀.

15. Ọ̀lẹ ti ọwọ́ bọ àwo oúnjẹ,ṣugbọn ó lẹ kọjá kí ó lè bu oúnjẹ kí ó fi bọ ẹnu.

16. Ọ̀lẹ gbọ́n lójú ara rẹ̀ju eniyan meje tí wọ́n lè dáhùn ọ̀rọ̀ pẹlu ọgbọ́n lọ.

17. Ẹni tí ó ti ọrùn bọ ìjà tí kì í ṣe tirẹ̀,dàbí ẹni tí ó gbá ajá alájá létí mú.

18. Bíi aṣiwèrè tí ó ju igi iná tabi ọfà olóró,

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 26