Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 24:14-20 BIBELI MIMỌ (BM)

14. Mọ̀ dájú pé bẹ́ẹ̀ ni ọgbọ́n yóo rí fún ọ,bí o bá ní i, yóo dára fún ọ lẹ́yìn ọ̀la,ìrètí rẹ kò sì ní di asán.

15. Má lúgọ bí eniyan burúkú láti kó ilé olódodo,má fọ́ ilé rẹ̀.

16. Nítorí pé bí olódodo bá ṣubú léra léra nígbà meje, yóo tún dìde,ṣugbọn àjálù máa ń bi ẹni ibi ṣubú.

17. Má yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú,má sì jẹ́ kí inú rẹ dùn bí ó bá kọsẹ̀,

18. kí OLUWA má baà bínú sí ọ tí ó bá rí ọ,kí ó sì yí ojú ibinu rẹ̀ pada kúrò lára ọ̀tá rẹ.

19. Má ṣe kanra nítorí àwọn aṣebi,má sì ṣe jowú eniyan burúkú,

20. nítorí pé kò sí ìrètí fún ẹni ibi,a óo sì pa àtùpà eniyan burúkú.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 24