Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 24:10-16 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Bí o bá kùnà lọ́jọ́ ìpọ́njú,a jẹ́ pé agbára rẹ kò tó.

11. Gba àwọn tí wọ́n bá fẹ́ lọ pa sílẹ̀,fa àwọn tí wọ́n bá fẹ́ ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n,lọ sọ́dọ̀ àwọn apànìyàn pada.

12. Bí ẹ bá sọ pé ẹ kò mọ nǹkan nípa rẹ̀,ṣé ẹni tí ó mọ èrò ọkàn kò rí i?Ṣé ẹni tí ń pa ẹ̀mí rẹ mọ́ kò mọ̀,àbí kò ní san án fún eniyangẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀?

13. Ọmọ mi, jẹ oyin, nítorí pé ó dùn,oyin tí a fún láti inú afárá a sì máa dùn lẹ́nu.

14. Mọ̀ dájú pé bẹ́ẹ̀ ni ọgbọ́n yóo rí fún ọ,bí o bá ní i, yóo dára fún ọ lẹ́yìn ọ̀la,ìrètí rẹ kò sì ní di asán.

15. Má lúgọ bí eniyan burúkú láti kó ilé olódodo,má fọ́ ilé rẹ̀.

16. Nítorí pé bí olódodo bá ṣubú léra léra nígbà meje, yóo tún dìde,ṣugbọn àjálù máa ń bi ẹni ibi ṣubú.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 24