Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 23:7-20 BIBELI MIMỌ (BM)

7. nítorí ẹni tí ó máa fi ọkàn ṣírò owó oúnjẹ ni.Ó lè máa wí fún ọ pé, “Jẹ, kí o sì mu!”ṣugbọn kò dé inú rẹ̀.

8. O óo pọ gbogbo òkèlè tí o jẹ,gbogbo ọ̀rọ̀ dídùn tí o sọ yóo sì jẹ́ àsọdànù.

9. Má sọ̀rọ̀ létí òmùgọ̀,nítorí yóo gan ọgbọ́n tí ó wà ninu ọ̀rọ̀ tí o sọ.

10. Má ṣe hú ohun tí wọ́n rì mọ́lẹ̀ fi pa ààlà láti ìgbà àtijọ́,má sì gba ilẹ̀ ọmọ aláìníbaba;

11. nítorí pé Olùràpadà wọn lágbára,yóo gba ìjà wọn jà.

12. Fi ọkàn rẹ sí ẹ̀kọ́, kí o sì tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ ìmọ̀.

13. Bá ọmọde wí;bí o bá fi pàṣán nà án, kò ní kú.

14. Bí o bá fi pàṣán nà án,o óo gba ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́ ikú.

15. Ọmọ mi, bí o bá gbọ́n,inú mi yóo dùn.

16. N óo láyọ̀ ninu ọkàn minígbà tí o bá ń sọ òtítọ́.

17. Má ṣe ìlara àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,ṣugbọn máa bẹ̀rù OLUWA lọ́jọ́ gbogbo.

18. Dájúdájú, ọjọ́ ọ̀la rẹ yóo dára,ìrètí rẹ náà kò sì ní já sí òfo.

19. Fetí sí mi, ọmọ mi, kí o sì gbọ́n,darí ọkàn rẹ sí ọ̀nà títọ́.

20. Má bá àwọn ọ̀mùtí kẹ́gbẹ́;tabi àwọn wọ̀bìà, tí wọn ń jẹ ẹran ní àjẹkì;

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 23