Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 23:11-22 BIBELI MIMỌ (BM)

11. nítorí pé Olùràpadà wọn lágbára,yóo gba ìjà wọn jà.

12. Fi ọkàn rẹ sí ẹ̀kọ́, kí o sì tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ ìmọ̀.

13. Bá ọmọde wí;bí o bá fi pàṣán nà án, kò ní kú.

14. Bí o bá fi pàṣán nà án,o óo gba ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́ ikú.

15. Ọmọ mi, bí o bá gbọ́n,inú mi yóo dùn.

16. N óo láyọ̀ ninu ọkàn minígbà tí o bá ń sọ òtítọ́.

17. Má ṣe ìlara àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,ṣugbọn máa bẹ̀rù OLUWA lọ́jọ́ gbogbo.

18. Dájúdájú, ọjọ́ ọ̀la rẹ yóo dára,ìrètí rẹ náà kò sì ní já sí òfo.

19. Fetí sí mi, ọmọ mi, kí o sì gbọ́n,darí ọkàn rẹ sí ọ̀nà títọ́.

20. Má bá àwọn ọ̀mùtí kẹ́gbẹ́;tabi àwọn wọ̀bìà, tí wọn ń jẹ ẹran ní àjẹkì;

21. nítorí pé àwọn ọ̀mùtí ati àwọn wọ̀bìà yóo di talaka,oorun àsùnjù a sì máa sọ eniyan di alákìísà.

22. Gbọ́ ti baba tí ó bí ọ,má sì ṣe pẹ̀gàn ìyá rẹ nígbà tí àgbà bá dé sí i.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 23