Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 23:1-6 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Nígbà tí o bá jókòó láti bá ìjòyè jẹun,kíyèsí ẹni tí ó bá wà níwájú rẹ dáradára.

2. Tí o bá jẹ́ wọ̀bìà eniyan, ṣọ́ra,kí o má fi ọ̀bẹ lé ara rẹ lọ́fun.

3. Má jẹ́ kí oúnjẹ aládìídùn rẹ̀ wọ̀ ọ́ lójú,nítorí ó lè jẹ́ oúnjẹ ẹ̀tàn.

4. Má ṣe làálàá àṣejù láti kó ọrọ̀ jọ,fi ọgbọ́n sẹ́ ara rẹ.

5. Kí o tó ṣẹ́jú pẹ́, owó rẹ lè ti lọ,ó le gúnyẹ̀ẹ́ kí ó fò,bí ìgbà tí ẹyẹ àṣá bá fò lọ.

6. Má ṣe jẹ oúnjẹ ahun,má ní ìfẹ́ sí oúnjẹ aládìídùn rẹ̀;

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 23