11. Ọmọde pàápàá a máa fi irú eniyan tí òun jẹ́ hàn nípa ìṣe rẹ̀,bí ohun tí ó ṣe dára, tí ó sì tọ̀nà.
12. Ati etí tí ń gbọ́ràn, ati ojú tí ń ríran,OLUWA ló dá ekinni-keji wọn.
13. Má fẹ́ràn oorun àsùnjù, kí o má baà di talaka,lajú, o óo sì ní oúnjẹ ní àníṣẹ́kù.
14. “Èyí kò dára, kò dára” ni ẹni tí ń rajà máa ń wí,bí ó bá lọ tán, a máa fọ́nnu ọjà ọ̀pọ̀ tí ó rà.
15. Wúrà ń bẹ, òkúta olówó iyebíye sì wà lọpọlọpọ,ṣugbọn ọ̀rọ̀ ìmọ̀ ni ohun ọ̀ṣọ́ olówó iyebíye.
16. Gba ẹ̀wù ẹni tí ó bá ṣe onídùúró fún àlejò,gba aṣọ ẹni tí ó ṣe onígbọ̀wọ́ ẹni tí kò mọ̀ rí.
17. Oúnjẹ tí a bá rí lọ́nà èrú máa ń dùn lẹ́nu eniyan,ṣugbọn nígbà tí a bá jẹ ẹ́ tán, ẹnu ẹni a máa kan.
18. Ìmọ̀ràn níí fìdí ètò múlẹ̀,gba ìtọ́sọ́nà kí o tó lọ jagun.
19. Ẹni tí ó ń ṣe òfófó káàkiri a máa tú ọpọlọpọ àṣírí,nítorí náà má ṣe bá ẹlẹ́jọ́ kẹ́gbẹ́.
20. Bí eniyan bá ń fi baba tabi ìyá rẹ̀ bú,àtùpà rẹ̀ yóo kú láàrin òkùnkùn biribiri.
21. Ogún tí a fi ìkánjú kójọ níbẹ̀rẹ̀,kì í ní ibukun nígbẹ̀yìn.
22. Má sọ pé o fẹ́ fi burúkú san burúkú,gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, yóo sì gbà ọ́.
23. Ayédèrú òṣùnwọ̀n jẹ́ ohun ìríra lójú OLUWA,ìwọ̀n èké kò dára.
24. OLUWA ní ń tọ́ ìṣísẹ̀ ẹni,eniyan kò lè ní òye ọ̀nà ara rẹ̀.
25. Ronú jinlẹ̀ kí o tó jẹ́jẹ̀ẹ́ fún OLUWA,kí o má baà kábàámọ̀ rẹ̀.
26. Ọba tó gbọ́n a máa fẹ́ eniyan burúkú dànù,a sì lọ̀ wọ́n mọ́lẹ̀.