Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 20:1-8 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ẹlẹ́yà ni ọtí waini,aláriwo ní ọtí líle,ẹnikẹ́ni tí a bá fi tànjẹ kò gbọ́n.

2. Ibinu ọba dàbí bíbú kinniun,ẹni tí ó bá mú ọba bínú fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu.

3. Nǹkan iyì ni pé kí eniyan máa yẹra fún ìjà,ṣugbọn òmùgọ̀ eniyan níí máa ń jà.

4. Ọ̀lẹ kì í dáko ní àkókò,nítorí náà, nígbà ìkórè, kò ní rí nǹkankan kó jọ.

5. Èrò ọkàn eniyan dàbí omi jíjìn,ẹni tí ó bá ní ìmọ̀ ló lè fà á jáde.

6. Ọ̀pọ̀ eniyan a máa ka ara wọn kún olóòótọ́,ṣugbọn níbo la ti lè rí ẹyọ ẹnìkan tó jẹ́ olódodo?

7. Olódodo a máa rìn ní ọ̀nà òtítọ́,ibukun ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ tí wọ́n tẹ̀lé e.

8. Nígbà tí ọba bá jókòó sórí ìtẹ́ ìdájọ́ rẹ̀,ojú ni yóo fi gbọn àwọn ẹni ibi dànù.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 20