Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 2:4-15 BIBELI MIMỌ (BM)

4. bí o bá wá ọgbọ́n bí ẹni ń wá fadaka,tí o sì wá a bí ẹni ń wá ìṣúra tí a pamọ́,

5. nígbà náà ni ìbẹ̀rù OLUWA yóo yé ọ.O óo sì rí ìmọ̀ Ọlọrun.

6. Nítorí OLUWA níí fún ni ní ọgbọ́n,ẹnu rẹ̀ sì ni òye ati ìmọ̀ ti ń wá.

7. Ó fún àwọn tí wọn dúró ṣinṣin ní ìjìnlẹ̀ ọgbọ́n,òun ni ààbò fún àwọn tí wọ́n ń rin ọ̀nà ẹ̀tọ́.

8. Ó ń tọ́ wọn sí ìdájọ́ òtítọ́,ó sì ń pa ọ̀nà àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀ mọ́.

9. Nígbà náà ni ìtumọ̀ òdodo ati ẹ̀tọ́ yóo yé ọati àìṣe ojuṣaaju, ati gbogbo ọ̀nà rere.

10. Nítorí ọgbọ́n yóo wọnú ọkàn rẹ,ìmọ̀ yóo sì tu ẹ̀mí rẹ lára,

11. ọgbọ́n inú yóo máa ṣọ́ ọ,òye yóo sì máa dáàbò bò ọ́,

12. yóo máa gbà ọ́ lọ́wọ́ ibi ṣíṣe,ati lọ́wọ́ àwọn ẹlẹ́tàn,

13. àwọn tí wọ́n ti kọ ọ̀nà òdodo sílẹ̀tí wọn sì ń rìn ninu òkùnkùn;

14. àwọn tí wọn ń yọ̀ ninu ìwà ibití wọ́n sì ní inú dídùn sí ìyapa ibi;

15. àwọn tí ọ̀nà wọn wọ́,tí wọ́n kún fún ìwà àrékérekè.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 2