Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 19:2-11 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Kò dára kí eniyan wà láìní ìmọ̀,ẹni bá ń kánjú rìn jù a máa ṣìnà.

3. Nígbà tí ìwà òmùgọ̀ bá kó ìparun bá a,ọkàn rẹ̀ a máa bá OLUWA bínú.

4. Ọrọ̀ a máa mú kí eniyan ní ọpọlọpọ ọ̀rẹ́ titun,ṣugbọn àwọn ọ̀rẹ́ talaka a máa kọ̀ ọ́ sílẹ̀.

5. Ẹlẹ́rìí èké kò ní lọ láìjìyà,bẹ́ẹ̀ ni òpùrọ́ kò ní bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀san ibi.

6. Ọ̀pọ̀ eniyan níí máa ń wá ojurere ẹni tó lawọ́,gbogbo eniyan sì ni ọ̀rẹ́ ẹni tí ń fúnni lẹ́bùn.

7. Gbogbo àwọn arakunrin talaka ni wọ́n kórìíra rẹ̀,kí á má ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ ti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tí wọ́n jìnnà sí i!Ó fọ̀rọ̀ ẹnu fà wọ́n títí, sibẹ wọn kò súnmọ́ ọn.

8. Ẹni tí ó ní ọgbọ́n fẹ́ràn ara rẹ̀,ẹni tí ó bá sì ní òye, yóo ṣe rere.

9. Ẹlẹ́rìí èké kò ní lọ láìjìyà,ẹni tí ó ń pa irọ́ yóo parun.

10. Ìgbádùn kò yẹ òmùgọ̀,bẹ́ẹ̀ ni kò yẹ kí ẹrú jọba lórí àwọn ìjòyè.

11. Ọgbọ́n kì í jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n yára bínú,ògo rẹ̀ sì níláti fojú fo ẹ̀ṣẹ̀ dá.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 19