Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 14:8-20 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Ohun tí ó jẹ́ ọgbọ́n fún ọlọ́gbọ́nni pé kí ó kíyèsí ọ̀nà ara rẹ̀,ṣugbọn àìmòye àwọn òmùgọ̀ kún fún ìtànjẹ.

9. Àwọn òmùgọ̀ a máa fi ọ̀rọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ ṣe àwàdà,ṣugbọn àwọn olódodo a máa rí ojurere.

10. Kálukú ló mọ ìbànújẹ́ ọkàn ara rẹ̀,kò sì sí àjèjì tí ń báni pín ninu ayọ̀.

11. Ìdílé ẹni ibi yóo parun,ṣugbọn ilé olódodo yóo máa gbèrú títí lae.

12. Ọ̀nà kan wà tí ó dàbí ẹni pé ó tọ́ lójú eniyan,ṣugbọn òpin rẹ̀, ikú ni.

13. Eniyan lè máa rẹ́rìn-ín, kí inú rẹ̀ má dùn,ìbànújẹ́ sì le gbẹ̀yìn ayọ̀.

14. Alágàbàgebè yóo jèrè iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ lẹ́kùn-únrẹ́rẹ́,ẹni rere yóo sì jèrè ìwà rere rẹ̀.

15. Òpè eniyan a máa gba ohun gbogbo gbọ́,ṣugbọn ọlọ́gbọ́n a máa kíyèsí ibi tí ó ń lọ.

16. Ọlọ́gbọ́n a máa ṣọ́ra, a sì máa sá fún ibi,ṣugbọn òmùgọ̀ kì í rọra ṣe, kì í sì í bìkítà.

17. Onínúfùfù a máa hùwà òmùgọ̀,ṣugbọn onílàákàyè a máa ní sùúrù.

18. Àwọn òpè a máa jogún àìgbọ́n,ṣugbọn àwọn ọlọ́gbọ́n a máa dé adé ìmọ̀.

19. Àwọn ẹni ibi yóo tẹríba fún àwọn ẹni rere,àwọn eniyan burúkú yóo sì tẹríba lẹ́nu ọ̀nà àwọn olódodo.

20. Àwọn aládùúgbò talaka pàápàá kórìíra rẹ̀,ṣugbọn ọlọ́rọ̀ a máa ní ọpọlọpọ ọ̀rẹ́.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 14