Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 14:19-32 BIBELI MIMỌ (BM)

19. Àwọn ẹni ibi yóo tẹríba fún àwọn ẹni rere,àwọn eniyan burúkú yóo sì tẹríba lẹ́nu ọ̀nà àwọn olódodo.

20. Àwọn aládùúgbò talaka pàápàá kórìíra rẹ̀,ṣugbọn ọlọ́rọ̀ a máa ní ọpọlọpọ ọ̀rẹ́.

21. Ẹni tí ó kẹ́gàn aládùúgbò rẹ̀ dẹ́ṣẹ̀,ṣugbọn ayọ̀ ń bẹ fun ẹni tí ó bá ṣàánú talaka.

22. Àwọn tí wọn ń pète ibi ti ṣìnà,ṣugbọn àwọn tí wọn ń gbèrò ire yóo rí ojurere ati òtítọ́.

23. Kò sí iṣẹ́ kan tí kò lérè,ṣugbọn ọ̀rọ̀ ẹnu lásán láìsí iṣẹ́, a máa sọ eniyan di aláìní.

24. Ọgbọ́n ni adé àwọn ọlọ́gbọ́n,ṣugbọn ìwà aláìgbọ́n jẹ́ yẹ̀yẹ́ àwọn òmùgọ̀.

25. Ẹlẹ́rìí tòótọ́ a máa gba ẹ̀mí là,ṣugbọn ọ̀dàlẹ̀ ni òpùrọ́.

26. Ninu ìbẹ̀rù OLUWA ni igbẹkẹle tí ó dájú wà,níbẹ̀ ni ààbò wà fún àwọn ọmọ ẹni.

27. Ìbẹ̀rù OLUWA ni orísun ìyè,òun níí mú ká yẹra fún tàkúté ikú.

28. Ọ̀pọ̀ eniyan ni ògo ọba,olórí tí kò bá ní eniyan yóo parun.

29. Ẹni tí kì í báá yára bínú lóye lọpọlọpọ,ṣugbọn onínúfùfù ń fi ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ hàn.

30. Ìbàlẹ̀ ọkàn a máa mú kí ara dá ṣáṣá,ṣugbọn ìlara a máa dá egbò sinu eegun.

31. Ẹni tí ó bá ni talaka lára àbùkù Ẹlẹ́dàá rẹ̀ ni ó ń ta,ṣugbọn ẹni tí ó ṣàánú fún àwọn aláìní ń bu ọlá fún Ẹlẹ́dàá rẹ̀.

32. Eniyan burúkú ṣubú nítorí ìwà ibi rẹ̀,ṣugbọn olódodo rí ààbò nípasẹ̀ òtítọ́ inú rẹ̀.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 14