Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 11:7-11 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Nígbà tí àwọn eniyan burúkú bá kú,ìrètí wọn yóo di asán,bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn tí kò mọ Ọlọrun yóo di òfo.

8. OLUWA a máa gba olódodo lọ́wọ́ ìyọnu,ṣugbọn ẹni ibi a bọ́ sinu wahala.

9. Ẹni tí kò mọ Ọlọrun a máafi ẹnu ba ti aládùúgbò rẹ̀ jẹ́,ṣugbọn nípa ìmọ̀ a máa gba olódodo sílẹ̀.

10. Nígbà tí nǹkan bá ń dára fún olódodo,gbogbo ará ìlú a máa yọ̀,nígbà tí eniyan burúkú bá kú,gbogbo ará ìlú a sì hó ìhó ayọ̀.

11. Ìre tí olódodo bá sú fún ìlú a máa gbé orúkọ ìlú ga,ṣugbọn ọ̀rọ̀ ẹnu àwọn eniyan burúkú a máa run ìlú.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 11