Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 10:19-31 BIBELI MIMỌ (BM)

19. Bí ọ̀rọ̀ bá ti pọ̀ jù, àṣìsọ a máa wọ̀ ọ́,ṣugbọn ẹni tí ó bá kó ẹnu ara rẹ̀ ní ìjánu, ọlọ́gbọ́n ni.

20. Ọ̀rọ̀ ẹnu olódodo dàbí fadaka,ṣugbọn èrò ọkàn eniyan burúkú kò já mọ́ nǹkankan.

21. Ọ̀rọ̀ ẹnu olódodo a máa ṣe ọpọlọpọ eniyan ní anfaani,ṣugbọn òmùgọ̀ eniyan a máa kú nítorí àìgbọ́n.

22. Ibukun OLUWA ní ń mú ni í là,kì í sì í fi làálàá kún un.

23. Ibi ṣíṣe a máa dùn mọ́ òmùgọ̀,ṣugbọn ìwà ọgbọ́n ni ayọ̀ fún ẹni tí ó mòye.

24. Ohun tí eniyan burúkú ń bẹ̀rù ni yóo dé bá a,ohun tí olódodo ń fẹ́ ni yóo sì rí gbà.

25. Nígbà tí ìjì líle bá ń jà, a gbá ẹni ibi lọ,ṣugbọn olódodo a fẹsẹ̀ múlẹ̀ títí lae.

26. Bí ọtí kíkan ti rí sí eyín,ati bí èéfín ti rí sí ojú,bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ rí sí ẹni tí ó bẹ̀ ẹ́ níṣẹ́.

27. Ìbẹ̀rù OLUWA a máa mú kí ẹ̀mí eniyan gùn,ṣugbọn ìgbé ayé eniyan burúkú yóo kúrú.

28. Ìrètí olódodo yóo yọrí sí ayọ̀,ṣugbọn ìrètí ẹni ibi yóo jásí òfo.

29. OLUWA jẹ́ agbára fún àwọn tí ọ̀nà wọn tọ́,ṣugbọn ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ibi.

30. Gbọningbọnin ni olódodo yóo dúró,ṣugbọn ẹni ibi kò ní lè gbé ilẹ̀ náà.

31. Ẹnu olódodo kún fún ọ̀rọ̀ ọgbọ́n,ṣugbọn ẹnu alaiṣootọ ni a pamọ́.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 10