Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Oníwàásù 11:2-7 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Gbin àwọn kan síhìn-ín, gbin àwọn kan sọ́hùn-ún, gbìn ín káàkiri oko nítorí o kò mọ ohun tí ó lè ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ọ̀la.

3. Nígbà tí òjò bá ṣú dẹ̀dẹ̀, orí ilẹ̀ ni yóo rọ̀ sí, níbi tí igi bá wó sí, níbẹ̀ náà ni yóo wà.

4. Ẹni tí ń wo ojú afẹ́fẹ́ kò ní fún irúgbìn kankan,ẹni tí ó bá sì ń wo ṣúṣú òjò kò ní kórè.

5. Gẹ́gẹ́ bí o kò ti mọ bí ẹ̀mí ṣe ń wọ inú ọmọ ninu aboyún, bẹ́ẹ̀ ni o kò mọ̀ bí Ọlọrun ṣe dá ohun gbogbo.

6. Fún irúgbìn ní àárọ̀, má sì ṣe dáwọ́ dúró ní ìrọ̀lẹ́, nítorí o kò mọ èyí tí yóo dàgbà, bóyá ti òwúrọ̀ ni tabi ti ìrọ̀lẹ́, tabi àwọn mejeeji.

7. Ìmọ́lẹ̀ dára, oòrùn sì dùn-ún wò.

Ka pipe ipin Ìwé Oníwàásù 11