Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkún Jeremaya 3:22-31 BIBELI MIMỌ (BM)

22. Nítorí pé Ìfẹ́ OLUWA tí kì í yẹ̀ kò nípẹ̀kun,àánú rẹ̀ kò sì lópin;

23. ọ̀tun ni wọ́n láràárọ̀,òtítọ́ rẹ̀ pọ̀.

24. Ọkàn mi wí pé, “OLUWA ni ìpín mi,nítorí náà lọ́dọ̀ rẹ̀ ni ìrètí mi wà.”

25. OLUWA a máa ṣe oore fún àwọn tí wọn dúró dè é,tí wọn sì ń wá ojurere rẹ̀.

26. Ó dára kí eniyan dúró jẹ́ẹ́, de ìgbàlà OLUWA.

27. Ó dára kí eniyan foríti àjàgà ìtọ́sọ́nà ní ìgbà èwe.

28. Kí ó fi ọwọ́ lẹ́rán, kí ó dákẹ́, kí ó sì máa wòye,nítorí Ọlọrun ni ó gbé àjàgà náà kọ́ ọ lọ́rùn.

29. Kí ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀,bóyá ìrètí lè tún wà fún un.

30. Kí ó kọ etí rẹ̀ sí ẹni tí ó fẹ́ gbá a létí,kí wọ́n sì fi àbùkù kàn án.

31. Nítorí OLUWA kò ní ta wá nù títí lae.

Ka pipe ipin Ẹkún Jeremaya 3