Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkún Jeremaya 3:15-29 BIBELI MIMỌ (BM)

15. Ó mú kí ọkàn mi kún fún ìbànújẹ́,ó fún mi ní iwọ mu ní àmuyó.

16. Ó fẹnu mi gbolẹ̀,títí yangí fi ká mi léyín;ó gún mi mọ́lẹ̀ ninu eruku

17. Ọkàn mi kò ní alaafia,mo ti gbàgbé ohun tí ń jẹ́ ayọ̀.

18. Nítorí náà, mo wí pé,“Ògo mi ti tán,ati gbogbo ohun tí mò ń retí lọ́dọ̀ OLUWA.”

19. Ranti ìyà ati ìbànújẹ́ mi,ati ìrora ọkàn mi!

20. Mò ń ranti nígbà gbogbo,ọkàn mi sì ń rẹ̀wẹ̀sì.

21. Ṣugbọn mo tún ń ranti nǹkankan,mo sì ní ìrètí.

22. Nítorí pé Ìfẹ́ OLUWA tí kì í yẹ̀ kò nípẹ̀kun,àánú rẹ̀ kò sì lópin;

23. ọ̀tun ni wọ́n láràárọ̀,òtítọ́ rẹ̀ pọ̀.

24. Ọkàn mi wí pé, “OLUWA ni ìpín mi,nítorí náà lọ́dọ̀ rẹ̀ ni ìrètí mi wà.”

25. OLUWA a máa ṣe oore fún àwọn tí wọn dúró dè é,tí wọn sì ń wá ojurere rẹ̀.

26. Ó dára kí eniyan dúró jẹ́ẹ́, de ìgbàlà OLUWA.

27. Ó dára kí eniyan foríti àjàgà ìtọ́sọ́nà ní ìgbà èwe.

28. Kí ó fi ọwọ́ lẹ́rán, kí ó dákẹ́, kí ó sì máa wòye,nítorí Ọlọrun ni ó gbé àjàgà náà kọ́ ọ lọ́rùn.

29. Kí ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀,bóyá ìrètí lè tún wà fún un.

Ka pipe ipin Ẹkún Jeremaya 3