Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkisodu 22:17-23 BIBELI MIMỌ (BM)

17. Bí baba wundia náà bá kọ̀ jálẹ̀ pé òun kò ní fi ọmọ òun fún un, yóo san iye owó tí wọ́n bá ń san ní owó orí wundia tí kò mọ ọkunrin.

18. “Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ́ kí àjẹ́ wà láàyè.

19. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ẹranko lòpọ̀, pípa ni kí wọ́n pa á.

20. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá rúbọ sí oriṣa-koriṣa kan lẹ́yìn OLUWA, píparun ni kí wọ́n pa á run.

21. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ pọ́n àlejò lójú tabi kí ó ni ín lára, nítorí pé ẹ̀yin náà ti jẹ́ àlejò rí ní ilẹ̀ Ijipti.

22. Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ fìyà jẹ opó tabi aláìníbaba.

23. Bí ẹnikẹ́ni bá fìyà jẹ wọ́n, tí wọ́n bá ké pè mí, dájúdájú n óo gbọ́ igbe wọn;

Ka pipe ipin Ẹkisodu 22