Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àwọn Ọba Kinni 9:21-28 BIBELI MIMỌ (BM)

21. arọmọdọmọ wọn tí wọ́n ṣẹ́kù, tí àwọn ọmọ Israẹli kò lè parun, ni Solomoni kó lẹ́rú pẹlu ipá, wọ́n sì wà bẹ́ẹ̀ títí di òní yìí.

22. Ṣugbọn Solomoni kò fi àwọn ọmọ Israẹli ṣe ẹrú. Àwọn ni ó ń lò gẹ́gẹ́ bí ọmọ ogun, ati olórí àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀; àwọn ni balogun rẹ̀, ati àwọn ọ̀gágun rẹ̀; àwọn ni ọ̀gá àwọn tí ń darí kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ ati àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.

23. Ẹgbẹta ó dín aadọta (550) ni àwọn lọ́gàálọ́gàá tí Solomoni fi ṣe alákòóso àwọn tí ó ń kó ṣiṣẹ́ tipátipá, níbi oríṣìíríṣìí iṣẹ́ ilé kíkọ́ rẹ̀.

24. Nígbà tí ó yá, ọmọ ọba Farao, iyawo Solomoni kó kúrò ní ìlú Dafidi, ó lọ sí ilé tí Solomoni kọ́ fún un. Lẹ́yìn náà ni Solomoni kọ́ ìlú Milo.

25. Ẹẹmẹta lọ́dún ni Solomoni máa ń rú ẹbọ sísun ati ẹbọ alaafia lórí pẹpẹ tí ó kọ́ fún OLUWA, a sì máa sun turari níwájú OLUWA. Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe parí kíkọ́ ilé náà.

26. Solomoni kan ọpọlọpọ ọkọ̀ ojú omi ní Esiongeberi lẹ́bàá Eloti, ní etí Òkun Pupa ní ilẹ̀ Edomu.

27. Hiramu ọba fi àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀ tí wọ́n mọ̀ nípa ọkọ̀ ojú omi, lé àwọn ọkọ̀ náà, ó kó wọn rán àwọn iranṣẹ Solomoni sí i.

28. Wọ́n tu ọkọ̀ lọ sí ilẹ̀ Ofiri, wọ́n sì kó wúrà tí ó tó okoolenirinwo (420) ìwọ̀n talẹnti bọ̀ wá fún Solomoni ọba.

Ka pipe ipin Àwọn Ọba Kinni 9