Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àwọn Ọba Kinni 9:1-8 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Lẹ́yìn tí Solomoni ọba ti kọ́ ilé OLUWA ati ààfin rẹ̀ tán, ati gbogbo ilé tí ó fẹ́ kọ́.

2. OLUWA tún fi ara hàn án lẹẹkeji, bí ó ti fara hàn án ní Gibeoni,

3. ó wí fún un pé, “Mo ti gbọ́ adura ati ẹ̀bẹ̀ rẹ, mo sì ti ya ilé tí o kọ́ yìí sí mímọ́. Ibẹ̀ ni wọn óo ti máa sìn mí títí lae. N óo máa mójú tó o, n óo sì máa dáàbò bò ó nígbà gbogbo.

4. Bí o bá sìn mí tọkàntọkàn pẹlu òtítọ́ inú, gẹ́gẹ́ bí Dafidi, baba rẹ, ti ṣe, bí o bá ṣe gbogbo ohun tí mo pa láṣẹ fún ọ, tí o sì pa òfin ati ìlànà mi mọ́,

5. n óo fìdí ìjọba rẹ múlẹ̀ ní Israẹli, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣèlérí fún Dafidi, baba rẹ, pé arọmọdọmọ rẹ̀ ni yóo máa jọba lórí àwọn ọmọ Israẹli títí lae.

6. Ṣugbọn bí ìwọ tabi arọmọdọmọ rẹ bá yapa kúrò lẹ́yìn mi, tí ẹ bá ṣe àìgbọràn sí àwọn òfin ati ìlànà tí mo fi lélẹ̀ fún yín, tí ẹ bẹ̀rẹ̀ sí bọ oriṣa,

7. n óo mú àwọn ọmọ Israẹli kúrò lórí ilẹ̀ tí mo fún wọn, n óo sì kọ ilé ìsìn tí mo ti yà sí mímọ́ fún orúkọ mi sílẹ̀. Gbogbo ọmọ Israẹli yóo di ẹni àmúpòwe ati ẹlẹ́yà láàrin àwọn orílẹ̀-èdè yòókù.

8. Ilé yìí yóo di òkìtì àlàpà, yóo sì di ohun àwòyanu ati ẹ̀gàn fún gbogbo ẹni tí ó bá ń rékọjá lọ. Wọn óo máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Kí ló dé tí OLUWA fi ṣe báyìí sí ilẹ̀ yìí ati ilé yìí?’

Ka pipe ipin Àwọn Ọba Kinni 9