Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Amosi 5:1-8 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ẹ fetí sí orin arò tí mò ń kọ le yín lórí, ẹ̀yin ìdílé Israẹli:

2. Israẹli, ọdọmọbinrin, ṣubú,kò ní lè dìde mọ́ lae.Ó di ìkọ̀sílẹ̀ ní ilẹ̀ rẹ̀,kò sì sí ẹni tí yóo gbé e dìde.

3. OLUWA Ọlọrun ní: “Ninu ẹgbẹrun ọmọ ogun tí ìlú Israẹli kan bá rán jáde, ọgọrun-un péré ni yóo kù. Ninu ọgọrun-un tí ìlú mìíràn bá rán jáde, mẹ́wàá péré ni yóo kù.”

4. OLUWA ń sọ fún ilé Israẹli pé: “Ẹ wá mi, kí ẹ sì yè;

5. ẹ má lọ sí Bẹtẹli, ẹ má sì wọ Giligali, tabi kí ẹ kọjá lọ sí Beeriṣeba; nítorí a óo kó Giligali lọ sí oko ẹrú, Bẹtẹli yóo sì di asán.”

6. Ẹ wá OLUWA, kí ẹ sì yè; bí bẹ́ẹ̀ kọ́, yóo rọ̀jò iná sórí ilé Josẹfu, ati sí ìlú Bẹtẹli; kò sì ní sí ẹni tí yóo lè pa á.

7. Ẹ gbé! Ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé ẹ̀bi fún aláre, tí ẹ sì tẹ òdodo mọ́lẹ̀.

8. Ẹni tí ó dá àwọn ìràwọ̀ Pileiadesi ati Orioni,tí ó sọ òkùnkùn biribiri di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀,òun níí sọ ọ̀sán di òru;òun ni ó dá omi òkun sórí ilẹ̀,OLUWA ni orúkọ rẹ̀.

Ka pipe ipin Amosi 5