Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 9:4-13 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Nítorí pé ó ti ṣẹ́ àjàgà tí ó wọ̀ wọ́n lọ́rùn,ati ọ̀pá tí wọn fí ń ru ẹrù sí èjìká,ati kùmọ̀ àwọn tí ń fìyà jẹ wọ́n.Ó ti ṣẹ́ wọn, bí ìgbà tí ó ṣẹ́ ti àwọn ará Midiani.

5. Gbogbo bàtà àwọn ológun, tí ń kilẹ̀ lójú ogun,ati gbogbo ẹ̀wù tí wọ́n ti yí mọ́lẹ̀ ninu ẹ̀jẹ̀ ni a óo dáná sun,iná yóo sì jó wọn run.

6. Nítorí a bí ọmọ kan fún wa,a fún wa ní ọmọkunrin kan.Òun ni yóo jọba lórí wa.A óo máa pè é ní Ìyanu, Olùdámọ̀ràn,Ọlọrun alágbára, Baba ayérayé,Ọmọ-Aládé alaafia.

7. Ìjọba rẹ̀ yóo máa tóbi sí i,alaafia kò sì ní lópin ní ìjọba rẹ̀ lórí ìtẹ́ Dafidi.Yóo fìdí rẹ̀ múlẹ̀,yóo sì gbé e ró pẹlu ẹ̀tọ́ ati òdodo,láti ìgbà yìí lọ, títí ayérayé.Ìtara OLUWA àwọn ọmọ ogun ni yóo ṣe èyí

8. OLUWA ranṣẹ ìdájọ́ sí Jakọbu,àní, sórí àwọn ọmọ Israẹli.

9. Gbogbo eniyan ni yóo mọ̀,àwọn ará Efuraimu ati àwọn ará Samaria,àwọn tí wọn ń fọ́nnu pẹlu ìgbéraga pé:

10. Ṣé bíríkì ni wọ́n fi kọ́ àwọn ilé tí ó wó lulẹ̀?Òkúta gbígbẹ́ ni a óo fi tún wọn kọ́.Igi sikamore ni a fi kọ́ èyí tí wọ́n dà wó,ṣugbọn igi kedari dáradára ni a óo lò dípò wọn.

11. Nítorí náà OLUWA ti gbé ọ̀tá dìde sí wọn:Ó ti rú àwọn ọ̀tá wọn sókè sí wọn:

12. Àwọn ará Siria láti ìhà ìlà oòrùn,ati àwọn ará Filistia láti ìhà ìwọ̀ oòrùn;wọn óo gbé Israẹli mì.Sibẹsibẹ inú OLUWA kò rọ̀,bẹ́ẹ̀ ni kò dá ọwọ́ ìjà rẹ̀ dúró.

13. Sibẹsibẹ àwọn ọmọ Israẹli kò pada sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó jẹ wọ́n níyà,bẹ́ẹ̀ ni wọn kò wá OLUWA àwọn ọmọ-ogun.

Ka pipe ipin Aisaya 9