Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 66:1-5 BIBELI MIMỌ (BM)

1. OLUWA ní:“Ọ̀run ni ìtẹ́ mi,ayé ni àpótí ìtìsẹ̀ mi.Ilé tí ẹ kọ́ fún mi dà?Níbo sì ni ibi ìsinmi mi wà?

2. Ọwọ́ mi ni mo fi ṣe gbogbo nǹkan wọnyi,tèmi sì ni gbogbo wọn.Ẹni tí n óo kà kún,ni onírẹ̀lẹ̀ ati oníròbìnújẹ́ eniyan, tí ó ń wárìrì nítorí ọ̀rọ̀ mi.

3. “Ati ẹni tí ó pa mààlúù rúbọ,ati ẹni tí ó pa eniyan;kò sí ìyàtọ̀.Ẹni tí ó fi ọ̀dọ́ aguntan rúbọ,kò yàtọ̀ sí ẹni tí ó lọ́ ajá lọ́rùn pa.Ati ẹni tí ó fi ọkà rúbọ,ati ẹni tí ó fi ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ rúbọ,bákan náà ni wọ́n rí.Ẹni tí ó fi turari ṣe ẹbọ ìrántí,kò sì yàtọ̀ sí ẹni tí ó súre níwájú oriṣa.Wọ́n ti yan ọ̀nà tí ó wù wọ́n,wọ́n sì ń fi tọkàntọkàn sin ohun ìríra wọn.

4. Èmi náà óo sì yan ìjìyà fún wọn,n óo jẹ́ kí ẹ̀rù wọn pada sórí wọn.Nítorí pé nígbà tí mo pè wọ́n, ẹnikẹ́ni wọn kò dáhùn;nígbà tí mo sọ̀rọ̀ fún wọn, wọn kò gbọ́,wọ́n ṣe ohun tí ó burú lójú mi,wọ́n yan ohun tí inú mi kò dùn sí.”

5. Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ OLUWA,ẹ̀yin tí ẹ̀ ń wárìrì nítorí ọ̀rọ̀ rẹ̀:“Àwọn arakunrin yín tí wọn kórìíra yín,wọ́n tì yín síta nítorí orúkọ mi;wọ́n ní, ‘Jẹ́ kí OLUWA fi ògo rẹ̀ hàn,kí á lè rí ayọ̀ yín.’Ṣugbọn àwọn ni ojú yóo tì.

Ka pipe ipin Aisaya 66