Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 51:11-23 BIBELI MIMỌ (BM)

11. Àwọn tí OLUWA rà pada yóo pada wá,pẹlu orin ni wọn óo pada wá sí Sioni.Adé ayọ̀ ni wọn óo dé sórí,wọn óo láyọ̀, inú wọn yóo dùn;ìbànújẹ́ ati ẹ̀dùn wọn yóo sì fò lọ.

12. “Èmi fúnra mi ni mò ń tù ọ́ ninu,ta ni ọ́, tí o fi ń bẹ̀rù eniyan tí yóo kú?Ìwọ ń bẹ̀rù ọmọ eniyan tí a dá, bíi koríko.

13. O gbàgbé OLUWA ẹlẹ́dàá rẹ,tí ó ta ojú ọ̀run bí aṣọ,tí ó fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀.O wá ń fi gbogbo ọjọ́ ayé bẹ̀rù ibinu àwọn aninilára,nítorí wọ́n múra tán láti pa ọ́ run?Ibinu àwọn aninilára kò ní dé ọ̀dọ̀ rẹ mọ́.

14. Láìpẹ́, a óo tú àwọn tí a tẹ̀ lórí ba sílẹ̀.Wọn kò ní kú, wọn kò ní wọ inú isà òkú,wọn kò sì ní wá oúnjẹ tì.

15. “Nítorí èmi ni OLUWA, Ọlọrun rẹ,ẹni tí ó rú òkun sókè,tí ìgbì rẹ̀ fi ń pariwo;OLUWA àwọn ọmọ ogun ni orúkọ mi.

16. Mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ọ lẹ́nu,mo ti pa ọ́ mọ́ lábẹ́ òjìji ọwọ́ mi.Èmi ni mo fi ojú ọ̀run sí ipò rẹ̀,tí mo fi àwọn ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀,tí mo sì sọ fún ìlú Sioni pé, ‘Ẹ̀yin ni eniyan mi.’ ”

17. Jí, jí! Dìde, ìwọ Jerusalẹmu.Ìwọ tí o ti rí ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ibinu OLUWA,ìwọ tí OLUWA ti fi ibinu jẹ níyà,tí ojú rẹ wá ń pòòyì.

18. Kò sí ẹni tí yóo tọ́ ọ sọ́nà,ninu gbogbo àwọn ọmọ tí o ti bí,kò sí ẹni tí yóo fà ọ́ lọ́wọ́,ninu gbogbo ọmọ tí o tọ́ dàgbà.

19. Àjálù meji ló dé bá ọ,ta ni yóo tù ọ́ ninu:Ìsọdahoro ati ìparun, ìyàn ati ogun,ta ni yóo tù ọ́ ninu?

20. Àárẹ̀ mú àwọn ọmọ rẹ,wọ́n sùn káàkiri ní gbogbo òpópó,bí ìgalà tí ó bọ́ sinu àwọ̀n.Ibinu OLUWA rọ̀jò lé wọn lórí,àní ìbáwí Ọlọrun rẹ.

21. Nítorí náà, ẹ̀yin tí à ń fi ìyà jẹ, ẹ gbọ́ èyí;ẹ̀yin tí ẹ ti yó láì tíì mu ọtí,

22. Oluwa rẹ, àní OLUWA Ọlọrun rẹ, tí ń bẹ̀bẹ̀ fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn eniyan rẹ̀ ní,“Wò ó! Mo ti gba ife àmutagbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n lọ́wọ́ rẹ,O kò ní rí ibinu mi mọ́.

23. Àwọn tí ń dá ọ lóró ni yóo rí ibinu mi,àwọn tí ó wí fún ọ pé,‘Bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ kí á gba orí rẹ kọjá;’tí wọ́n sọ ẹ̀yìn rẹ di ilẹ̀ẹ́lẹ̀,tí wọ́n sọ ọ́ di ojú ọ̀nà wọn, tí wọn óo máa gbà kọjá.”

Ka pipe ipin Aisaya 51