Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 50:3-10 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Mo da òkùnkùn bo ojú ọ̀run bí aṣọ,mo ṣe aṣọ ọ̀fọ̀ ní ìbora fún wọn.”

4. OLUWA Ọlọrun ti fi ọ̀rọ̀ ìmọ̀ sí mi lẹ́nu.Kí n lè mọ bí a tií gba àwọn tí ọkàn wọn rẹ̀wẹ̀sì níyànjú.Ojoojumọ ni ó ń ṣí mi létí láràárọ̀,kí n lè máa gbọ́rọ̀ bí àwọn akẹ́kọ̀ọ́.

5. OLUWA Ọlọrun ti ṣí mi létí,n kò sì ṣe oríkunkun,tabi kí n pada sẹ́yìn.

6. Mo tẹ́ ẹ̀yìn sílẹ̀ fún àwọn tí ń nani lẹ́gba;mo sì kọ ẹ̀rẹ̀kẹ́ sí àwọn tí ń fa eniyan ní irùngbọ̀n tu.N kò fojú pamọ́ nítorí ẹ̀gàn,bẹ́ẹ̀ ni n kò gbójú sá fún itọ́ títu síni lójú.

7. OLUWA Ọlọrun ń ràn mí lọ́wọ́,nítorí náà ojú kò tì mí;nítorí náà mo múra gírí,mo jẹ́ kí ojú mi le koko,mo sì mọ̀ pé ojú kò ní tì mí.

8. Ẹni tí yóo dá mi láre wà nítòsí,ta ló fẹ́ bá mi jà?Ta ló fẹ́ fi ẹ̀sùn kàn mí?Kí olúwarẹ̀ súnmọ́ tòsí mi,kí á jọ kojú ara wa?

9. Wò ó! OLUWA Ọlọrun ń ràn mí lọ́wọ́,ta ni yóo dá mi lẹ́bi?Gbogbo wọn ni yóo gbọ̀n dànù bí aṣọ,kòkòrò yóo sì jẹ wọ́n.

10. Ta ló bẹ̀rù OLUWA ninu yín,tí ń gbọ́ràn sí iranṣẹ rẹ̀ lẹ́nu,tí ń rìn ninu òkùnkùn,tí kò ní ìmọ́lẹ̀,ṣugbọn sibẹ, tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA,tí ó fẹ̀yìn ti Ọlọrun rẹ̀.

Ka pipe ipin Aisaya 50