Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 40:9-16 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Gun orí òkè gíga lọ, ìwọ Sioni,kí o máa kéde ìyìn rere.Gbé ohùn rẹ sókè pẹlu agbára Jerusalẹmu,ìwọ tí ò ń kéde ìyìn rereké sókè má ṣe bẹ̀rù;sọ fún àwọn ìlú Juda pé,“Ẹ wo Ọlọrun yín.”

10. Ẹ wò ó! OLUWA Ọlọrun ń bọ̀ pẹlu agbáraipá rẹ̀ ni yóo fi máa ṣe àkóso.Ẹ wò ó! Èrè rẹ̀ ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, ẹ̀san rẹ̀ sì ń bẹ níwájú rẹ̀.

11. Yóo bọ́ agbo ẹran bí olùṣọ́-aguntan.Yóo kó àwọn ọ̀dọ́ aguntan jọ sí apá rẹ̀,yóo gbé wọn mọ́ àyà rẹ̀.Yóo sì máa fi sùúrù da àwọn tí wọn lọ́mọ lẹ́yìn láàrin wọn.

12. Ta ló lè fi kòtò ọwọ́ wọn omi òkun?Ta ló lè fìka wọn ojú ọ̀run,Kí ó kó erùpẹ̀ ilẹ̀ ayésinu òṣùnwọ̀n?Ta ló lè gbé àwọn òkè ńlá ati àwọn kéékèèké sórí ìwọ̀n?

13. Ta ló darí Ẹ̀mí OLUWA,ta ló sì tọ́ ọ sọ́nà gẹ́gẹ́ bí olùdámọ̀ràn rẹ̀?

14. Ọwọ́ ta ni OLUWA ti gba ìmọ̀ràn tí ó fi ní òye,ta ló kọ́ ọ bí wọ́n ṣe ń dájọ́ ẹ̀tọ́,tí ó kọ́ ọ ní ìmọ̀,tí ó sì fi ọ̀nà òye hàn án?

15. Wò ó, àwọn orílẹ̀-èdè dàbí ìkán omi kan ninu garawa omi,ati bí ẹyọ eruku kan lórí òṣùnwọ̀n.Ẹ wò ó, ó mú àwọn erékùṣù lọ́wọ́ bí àtíkè.

16. Gbogbo igi igbó Lẹbanoni kò tó fún iná ẹbọ,bẹ́ẹ̀ ni ẹranko ibẹ̀ kò tó fún ẹbọ sísun.

Ka pipe ipin Aisaya 40