Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 40:1-12 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ọlọrun yín ní, “Ẹ tù wọ́n ninu,ẹ tu àwọn eniyan mi ninu.

2. Ẹ bá Jerusalẹmu sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ẹ ké sí i pé, ogun jíjà rẹ̀ ti parí,a ti dárí àìṣedéédé rẹ̀ jì í.OLUWA ti jẹ ẹ́ níyà ní ìlọ́po meji nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.”

3. Ẹ gbọ́ ohùn akéde kan tí ń wí pé,“Ẹ tún ọ̀nà OLUWA ṣe ninu aginjù,ẹ la òpópónà títọ́ fún Ọlọrun wa ninu aṣálẹ̀.

4. Gbogbo àfonífojì ni a óo ru sókè,a óo sì sọ àwọn òkè ńlá ati òkè kéékèèké di pẹ̀tẹ́lẹ̀:Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ́ ni yóo di títọ́,ọ̀nà gbágun-gbàgun yóo sì di títẹ́jú.

5. Ògo OLUWA yóo farahàn,gbogbo eniyan yóo sì jọ fojú rí i.OLUWA ni ó fi ẹnu ara rẹ̀ sọ bẹ́ẹ̀.”

6. Mo gbọ́ ohùn kan tí ń wí pé, “Kígbe!”Mo bá bèèrè pé,“Igbe kí ni kí n ké?”Ó ní, “Kígbe pé, koríko ṣá ni gbogbo eniyan,gbogbo ẹwà sì dàbí òdòdó inú pápá.

7. Koríko a máa rọ, òdòdó a sì máa rẹ̀nígbà tí OLUWA bá fẹ́ afẹ́fẹ́ lù ú.Dájúdájú koríko ni eniyan.

8. Koríko a máa rọ,òdòdó a sì máa rẹ̀;ṣugbọn ọ̀rọ̀ Ọlọrun wa dúró títí lae.”

9. Gun orí òkè gíga lọ, ìwọ Sioni,kí o máa kéde ìyìn rere.Gbé ohùn rẹ sókè pẹlu agbára Jerusalẹmu,ìwọ tí ò ń kéde ìyìn rereké sókè má ṣe bẹ̀rù;sọ fún àwọn ìlú Juda pé,“Ẹ wo Ọlọrun yín.”

10. Ẹ wò ó! OLUWA Ọlọrun ń bọ̀ pẹlu agbáraipá rẹ̀ ni yóo fi máa ṣe àkóso.Ẹ wò ó! Èrè rẹ̀ ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, ẹ̀san rẹ̀ sì ń bẹ níwájú rẹ̀.

11. Yóo bọ́ agbo ẹran bí olùṣọ́-aguntan.Yóo kó àwọn ọ̀dọ́ aguntan jọ sí apá rẹ̀,yóo gbé wọn mọ́ àyà rẹ̀.Yóo sì máa fi sùúrù da àwọn tí wọn lọ́mọ lẹ́yìn láàrin wọn.

12. Ta ló lè fi kòtò ọwọ́ wọn omi òkun?Ta ló lè fìka wọn ojú ọ̀run,Kí ó kó erùpẹ̀ ilẹ̀ ayésinu òṣùnwọ̀n?Ta ló lè gbé àwọn òkè ńlá ati àwọn kéékèèké sórí ìwọ̀n?

Ka pipe ipin Aisaya 40