3. Àwọn orílẹ̀-èdè sá nígbà tí wọ́n gbọ́ ariwo tí ó dàbí ti ààrá,wọ́n fọ́n ká nígbà tí o gbéra nílẹ̀.
4. A kó ìkógun jọ bí ìgbà tí tata bo oko,àwọn eniyan dà bo ìṣúra, bí ìgbà tí eṣú bo oko.
5. A gbé OLUWA ga!Nítorí pé ibi gíga ni ó ń gbé;yóo mú kí ìdájọ́ òtítọ́ ati òdodo kún Sioni.
6. Yóo mú kí ìdúróṣinṣin wà ní gbogbo àkókò rẹ̀.Yóo fún ọ ní ọpọlọpọ ìgbàlà, ati ọgbọ́n, ati ìmọ̀,ìbẹ̀rù OLUWA ni ìṣúra rẹ̀.
7. Ẹ wò ó, àwọn alágbára ń kígbe lóde,àwọn òjíṣẹ́ alaafia ń sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn.
8. Òpópó ọ̀nà ṣófo,àwọn èrò kò rìn mọ́;wọ́n ń ba majẹmu jẹ́,wọn kò bìkítà fún ẹlẹ́rìí mọ́;wọ́n kò sì ka eniyan sí.
9. Ilẹ̀ ṣófo ó sì gbẹ,ìtìjú bá òkè Lẹbanoni,gbogbo ewéko orí rẹ̀ sì rẹ̀ dànù.Ṣaroni dàbí aṣálẹ̀,igi igbó Baṣani ati ti òkè Kamẹli sì wọ́wé.
10. OLUWA ní:“Ó yá tí n óo dìde,ó yá mi wàyí, n óo gbéra nílẹ̀.Àsìkò tó tí a óo gbé mi ga.
11. Èrò yín dàbí fùlùfúlù, gbogbo ìṣe yín dàbí pòpórò ọkà.Èémí mi yóo jó yín run bí iná.
12. Àwọn orílẹ̀-èdè yóo dàbí ìgbà tí a sun wọ́n,tí wọ́n di eérú,àní bí igi ẹ̀gún tí a gé lulẹ̀, tí a sì dáná sun.