Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 32:6-17 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Nítorí pé aláìgbọ́n ń sọ̀rọ̀ òmùgọ̀,ọkàn rẹ̀ sì ń pète ibi.Ó ń ro bí yóo ṣe hùwà ẹni tí kò mọ Ọlọrun,tí yóo sọ̀rọ̀ ìsọkúsọ sí OLUWA;tí yóo fi ẹni tí ebi ń pa sílẹ̀, láì fún un ní oúnjẹ,tí yóo sì fi omi du ẹni òùngbẹ ń gbẹ.

7. Kìkì ibi ni èrò inú àwọn eniyankeniyan.Wọn a máa pète ìkà,láti fi irọ́ pa àwọn talaka run,kì báà jẹ́ pé ẹjọ́ aláìní jàre.

8. Ṣugbọn eniyan rere a máa ro èrò rere,ìdí nǹkan rere ni à á sì í bá wọn.

9. Ẹ dìde, ẹ̀yin obinrin tí ara rọ̀,ẹ gbóhùn mi; ẹ̀yin ọmọbinrin tí ẹ wà ninu ìdẹ̀ra,ẹ tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi.

10. Ní nǹkan bíi ọdún kan ó lé díẹ̀ sí iẹ̀yin obinrin tí ẹ wà ninu ìdẹ̀ra; ẹ ó rí ìdààmúnítorí pé àkókò ìkórè yóo kọjá,èso àjàrà kò sì ní sí lórí igi mọ́.

11. Ẹ gbọ̀n jìnnìjìnnì, ẹ̀yin obinrin tí ara rọ̀,kí wahala ba yín, ẹ̀yin tí ẹ wà ninu ìdẹ̀ra,ẹ tú aṣọ yín, kí ẹ wà ní ìhòòhò;kí ẹ sì ró aṣọ ọ̀fọ̀.

12. Ẹ káwọ́ lérí, kí ẹ káàánú nítorí àwọn oko dáradára,ati nítorí àwọn àjàrà eléso;

13. nítorí ẹ̀gún ẹ̀wọ̀n ati ẹ̀gún ọ̀gàn ni ó ń hù lórí ilẹ̀ àwọn eniyan mi.Bákan náà, ẹ káàánú fún àwọn ilé aláyọ̀ ninu ìlú tí ó kún fún ayọ̀,

14. nítorí pé àwọn eniyan yóo sá kúrò ní ààfin,ìlú yóo tú, yóo di ahoro.Òkè ati ilé ìṣọ́ yóo di ibùgbé àwọn ẹranko títí lae,yóo di ibi ìgbádùn fún àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́,ati pápá ibùjẹ fún àwọn ẹran ọ̀sìn.

15. Bẹ́ẹ̀ ni nǹkan yóo rí,títí ẹ̀mí óo fi bà lé wa láti òkè ọ̀run wátítí aṣálẹ̀ yóo fi di ọgbà eléso,tí ọgbà eléso yóo sì fi di igbó.

16. A óo máa ṣe ìdájọ́ ẹ̀tọ́ ní gbogbo ilẹ̀ náà,ìwà òdodo yóo sì wà níbi gbogbo.

17. Àyọrísí òdodo yóo sì jẹ́ alaafia,ìgbẹ̀yìn rẹ̀ yóo sì jẹ́ ìbàlẹ̀ àyà wa,ati igbẹkẹle OLUWA títí lae.

Ka pipe ipin Aisaya 32