Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 28:5-16 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Ní ọjọ́ náà,OLUWA àwọn ọmọ ogun yóo jẹ́ adé ògo ati adé ẹwà,fún àwọn tí ó kù ninu àwọn eniyan rẹ̀.

6. Yóo jẹ́ ẹ̀mí ìdájọ́ ẹ̀tọ́fún adájọ́ tí ó jókòó lórí ìtẹ́ ìdájọ́,yóo jẹ́ agbára fún àwọn tí ó ń lé ogun sẹ́yìn lẹ́nu ibodè.

7. Ọtí waini ń ti àwọn wọnyi,ọtí líle ń mú wọn ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n.Ọtí líle ń ti alufaa ati wolii,ọtí waini kò jẹ́ kí wọ́n mọ ohun tí wọ́n ń ṣe mọ́.Ọtí líle ń mú wọn ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n;wọ́n ń ríran èké, wọ́n ń dájọ́ irọ́.

8. Nítorí èébì kún orí gbogbo tabili oúnjẹ,gbogbo ilẹ̀ sì kún fún ìdọ̀tí

9. Wọ́n ń sọ pé, “Ta ni yóo kọ́ lọ́gbọ́n?Ta sì ni yóo jíṣẹ́ náà fún?Ṣé àwọn tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ gbọyàn lẹ́nu wọn,àbí àwọn tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ já lẹ́nu ọmú?

10. Nítorí pé gbogbo rẹ̀ tòfin-tòfin ni,èyí òfin, tọ̀hún ìlànà.Díẹ̀ níhìn-ín, díẹ̀ lọ́hùn-ún.”

11. Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, àwọn àjèjì tí èdè wọn yàtọ̀ ni OLUWA yóo lòláti bá àwọn eniyan wọnyi sọ̀rọ̀.

12. Àwọn tí ó ti wí fún pé:Ìsinmi nìyí,ẹ fún àwọn tí àárẹ̀ mú ní ìsinmi;ìtura nìyí.Sibẹsibẹ wọ́n kọ̀, wọn kò gbọ́.

13. Nítorí náà ọ̀rọ̀ OLUWA sí wọn yóo jẹ́ tòfin-tòfin,èyí òfin tọ̀hún ìlànà.Díẹ̀ níhìn-ín, díẹ̀ lọ́hùn-ún,kí wọ́n baà lè lọ ṣubú sẹ́yìnkí wọ́n sì fọ́ wẹ́wẹ́;kí á lè dẹ tàkúté sílẹ̀ fún wọn,kí ọwọ́ lè tẹ̀ wọ́n.

14. Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí OLUWA wí,ẹ̀yin oníyẹ̀yẹ́ eniyan,tí ẹ̀ ń ṣe àkóso àwọn eniyan wọnyi ní Jerusalẹmu.

15. Nítorí ẹ wí pé:“A ti bá ikú dá majẹmu,a sì ti bá ibojì ṣe àdéhùn.Nígbà tí jamba bá ń bọ̀,kò ní dé ọ̀dọ̀ wa;nítorí a ti fi irọ́ ṣe ibi ìsádi wa,a sì ti fi èké ṣe ibi ààbò.”

16. Nítorí náà OLUWA Ọlọrun sọ pé,“Wò ó! Èmi yóo ri òkúta ìpìlẹ̀ ilé kan mọ́lẹ̀ ní Sioni,yóo jẹ́ òkúta tí ó lágbára,òkúta igun ilé iyebíye, tí ó ní ìpìlẹ̀ tí ó dájú:Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, ojú kò níí kán an.

Ka pipe ipin Aisaya 28