Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 14:5-19 BIBELI MIMỌ (BM)

5. OLUWA ti ṣẹ́ ọ̀pá àṣẹ àwọn ẹni ibi,ati ọ̀pá àṣẹ àwọn olórí

6. tí wọn ń fi ibinu lu àwọn eniyan láì dáwọ́ dúró,tí wọn ń fi ibinu ṣe àkóso àwọn orílẹ̀-èdè,tí ó ń ṣe inúnibíni lemọ́lemọ́.

7. Gbogbo ayé wà ní ìsinmi ati alaafiawọ́n bẹ̀rẹ̀ sí kọ orin ayọ̀.

8. Àwọn igi Sipirẹsi ń yọ̀ yín;àwọn igi Kedari ti Lẹbanoni sì ń sọ pé,‘Láti ìgbà tí a ti rẹ ọba Babiloni sílẹ̀,kò sí agégi kan tí ó wá dààmú wa mọ́.’

9. “Isà òkú ti lanu sílẹ̀ láti pàdé rẹ bí o bá ti ń dé.Ó ta àwọn òkú ọ̀run jí láti kí ọ,àwọn tí wọ́n ṣe pataki ní àkókò wọn,Ó gbé gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè dìde lórí ìtẹ́ wọn.

10. Gbogbo wọn yóo wí fún ọ pé,‘Àárẹ̀ ti mu yín gẹ́gẹ́ bí ó ti mú àwa náà.Ẹ ti dàbí i wa.

11. A ti fa ògo yín ati ohùn hapu yín sinu isà òkú.Ìdin di ibùsùn tí ẹ sùn lé lóríàwọn kòkòrò ni ẹ sì fi bora bí aṣọ.’

12. “Ọba Babiloni, wò ó! Bí o ti jábọ́ láti ojú ọ̀run,ìwọ tí o dàbí ìràwọ̀ òwúrọ̀!Wò ó bí a ti sọ ọ́ di ẹni ilẹ̀,ìwọ tí o ti pa ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè run rí.

13. Ó pinnu lọ́kàn ara rẹ̀ pé,‘N óo gòkè dé ọ̀run,n óo gbé ìtẹ́ mi kọjá àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run;n óo jókòó lórí òkè àpéjọ àwọn eniyan,ní ìhà àríwá ní ọ̀nà jíjìn réré.

14. N óo gòkè kọjá ìkùukùu ojú ọ̀run,n óo wá dàbí Olodumare.’

15. Ṣugbọn a já ọ lulẹ̀ sinu isà òkú,sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun.

16. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá rí ọ yóo tẹjú mọ́ ọ,wọ́n óo fi ọ́ ṣe àríkọ́gbọ́n pé,‘Ṣé ọkunrin tí ó ń kó ìpayà bá gbogbo ayé nìyí,tí ó ń mi àwọn orílẹ̀-èdè jìgìjìgì;

17. ẹni tí ó sọ ayé di aṣálẹ̀,tí ó sì pa àwọn ìlú ńláńlá rẹ̀ run,ẹni tí kì í dá àwọn tí ó bá wà ní ìgbèkùn rẹ̀ sílẹ̀?’

18. Gbogbo ọba àwọn orílẹ̀-èdè dùbúlẹ̀ ninu ògo wọnolukuluku ninu ibojì tirẹ̀.

19. Ṣugbọn a lé ìwọ kúrò ninu ibojì rẹ,bí ọmọ tí a bí kí oṣù rẹ̀ tó pé,tí a gbé òkú rẹ̀ sọnù;tí a jù sáàrin òkú àwọn jagunjagun tí a pa lójú ogun;àwọn tí a jù sinu kòtò olókùúta,bí àwọn tí a tẹ̀ ní àtẹ̀pa.

Ka pipe ipin Aisaya 14