Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Róòmù 9:17-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Nítorí ìwé mímọ́ wí fún Fáráò pé, Nítorí èyí ni mo ṣe gbé ọ dìde, kí èmi kí ó le fi agbára mi hàn lára rẹ, kí a sì le máa ròyìn orúkọ mi ká gbogbo ayé.

18. Nítorí náà ni ó ṣe sàánú fún ẹni tí ó wù ú, ẹni tí ó wù ú a sì mú lí ọkàn le.

19. Ìwọ ó sì wí fún mi pé, kínni ó ha tún bá ni wí fún? Nítorí tani ó ń de ìfẹ́ rẹ lọ́nà?

20. Bẹ́ẹ̀ kọ́, Ìwọ ènìyàn, tà ni ìwọ tí ń dá Ọlọ́run lóhùn? Ohun tí a mọ, a máa wí fún ẹni tí ó mọ ọn pé, Èéṣe tí ìwọ fi mọ mi báyì?

21. Amọ̀kòkò kò ha ni agbára lórí àmọ̀, níní ìṣu kan náà láti ṣe apákan ní ohun èlò sí ọlá, àti apákan ní ohun èlò sí àìlọ́lá?

22. Ǹjẹ́ bí Ọlọ́run bá fẹ́ fi ìbínú rẹ̀ hàn ń kọ́? Tí ó sì fẹ́ sọ agbára rẹ̀ di mímọ̀, tí ó sì mú sùúrù púpọ̀ fún àwọn ohun èlò ìbínú tí a ṣe fún ìparun;

23. Àti kí ó lè sọ ọ̀rọ̀ ògo rẹ̀ di mímọ̀ lára àwọn ohun èlò àánú tí ó ti pèsè ṣájú fún ògo,

24. Àní àwa, tí ó ti pè, kì í ṣe nínú àwọn Júù nìkan, ṣùgbọ́n nínú àwọn aláìkọlà pẹ̀lú?

25. Bí ó ti wí pẹ̀lú ní Hóséà pé,“Èmi ó pe àwọn tí kì í ṣe ènìyàn mi, ní ènìyàn mi,àti ẹni tí kí í ṣe àyànfẹ́ ní àyànfẹ́.”

26. Yóò sì ṣe,“Ní ibi ti a gbé ti sọ fún wọn pé,‘ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’níbẹ̀ ni a ó gbé ti sọ fún wọn pé,ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,níbẹ̀ ni a ó gbé pè wọ́n ní ‘ọmọ Ọlọ́run alààyè.’ ”

27. Ìsáíà sì kí gbe nnítorí Ísírẹ́lì pé:“Bí iye àwọn ọmọ Ísírẹ́lì bá rí bí iyanrìn etí òkun,apákan ni ó gbàlà.

28. Nítorí Olúwa yóò mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ lórí ilẹ̀ ayé,yóò parí rẹ̀, yóò sì ké e kúrò ní òdodo.”

29. Àti bí Ìsáià ti wí tẹ́lẹ̀:“Bí kò ṣe bí Olúwa àwọnỌmọ-ogun ti fi irú-ọmọ sílẹ̀ fún wa,àwa ìbá ti dàbí Sódómù,a bá sì ti sọ wá dàbí Gòmórà.”

30. Ǹjẹ́ kílí àwa ó ha wí? Pé àwọn aláìkọlà, tí kò lépa òdodo, ọwọ́ wọn tẹ òdodo, ṣùgbọ́n òdodo tí ó ti inú ìgbàgbọ́ wá ni.

31. Ṣùgbọ́n Ísírẹ́lì ti ń lépa òfin òdodo, ọwọ́ wọn kò tẹ òfin òdodo,

32. Nítorí kíni? Nítorí wọn kò wá a nípa ìgbàgbọ́, ṣùgbọ́n bí ẹni pé nípa iṣẹ́ òfin. Nítorí wọn kọsẹ̀ lára òkúta ni;

Ka pipe ipin Róòmù 9