Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Róòmù 9:14-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Njẹ́ àwa yóò ha ti wí? Àìsòdodo ha wà lọ́dọ̀ Ọlọ́run bí? Kí a má ri!

15. Nítorí ó wí fún Mósè pé,“Èmi ó sàánú fún ẹni tí èmi yóò sàánú fún,èmi yóò sì se ìyọ́nú fún ẹni tí èmi yóò se ìyọ́nú fún.”

16. Ǹjẹ́ bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe ti ẹni tí ó fẹ́, kì í sì í se ti ẹni tí ń sáré, bí kò se ti Ọlọ́run tí ń sàánú.

17. Nítorí ìwé mímọ́ wí fún Fáráò pé, Nítorí èyí ni mo ṣe gbé ọ dìde, kí èmi kí ó le fi agbára mi hàn lára rẹ, kí a sì le máa ròyìn orúkọ mi ká gbogbo ayé.

18. Nítorí náà ni ó ṣe sàánú fún ẹni tí ó wù ú, ẹni tí ó wù ú a sì mú lí ọkàn le.

19. Ìwọ ó sì wí fún mi pé, kínni ó ha tún bá ni wí fún? Nítorí tani ó ń de ìfẹ́ rẹ lọ́nà?

Ka pipe ipin Róòmù 9