Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Róòmù 6:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ǹjẹ́ àwa ó ha ti wí? Ṣé kí àwa ó jòkòó nínú ẹ̀ṣẹ̀, kí oore-ọ̀fẹ́ ba à lè máa pọ̀ sí i?

2. Kò lè rí bẹ́ẹ̀. Ṣé a tún le máa dẹ́sẹ̀ lẹ́yìn tí a ti fún wa ní ìṣẹ́gun lórí rẹ̀?

3. Nítorí a ti ṣẹ́gun agbára ẹ̀ṣẹ̀ nígbà tí a di Kírísítẹ́nì tí a sì ṣe ìrìbọmi fún wa láti di apá kan Jésù Kírísítì nípasẹ̀ ikú rẹ̀, a borí agbára ìwà ẹ̀ṣẹ̀.

4. Ẹ ti gbé ògbólógbòó ara yín tí ń fẹ́ máa dẹ́sẹ̀ sin pẹ̀lú Kírísítì nígbà tí òun kú, àti nígbà tí Ọlọ́run Baba pẹ̀lú agbára ògo mú un padà sí ìyè, a sì fún yín ní ìyè tun tun rẹ̀ láti gbádùn rẹ̀, èyí ṣẹlẹ̀ nípa ìrìbọmi yín.

5. Nítorí pé ẹ̀yin ti di apá kan ara rẹ̀, àti pé ẹ kú pẹ̀lú rẹ̀, nígbà tí òun kú. Nísinsin yìí, ẹ ń pín ìyè tuntun rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì jí dìde gẹ́gẹ́ bí òun náà ti jí dìde.

Ka pipe ipin Róòmù 6