Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Róòmù 5:2-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Nípasẹ̀ ẹni tí àwa sì ti rí ọ̀nà gbà nípa ìgbàgbọ́ sí inú oore-ọ̀fẹ́ yìí nínú èyí tí àwa gbé dúró. Àwa sì ń yọ̀ nínú ìrètí ògo Ọlọ́run.

3. Kì í sì ṣe bẹ́ẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n àwa tún ń ṣògo nínú ìjìyà pẹ̀lú: bí a ti mọ̀ pé ìjìyà ń sisẹ́ sùúrù;

4. Àti pé sùúrù ń siṣẹ́ ìrírí; àti pé ìrírí ń siṣẹ́ ìrètí:

5. Ìrètí kì í sì í dójútini nítorí a ti dá ìfẹ́ Ọlọ́run sí wa lọ́kàn láti ọwọ́ Ẹ̀mí Mímọ́ tí a fi fún wa.

6. Nítorí ìgbà tí àwa jẹ́ aláìlera, ní àkókò tí ó yẹ, Kírísítì kú fún àwa aláìwà-bí-Ọlọ́run.

Ka pipe ipin Róòmù 5