8. Tàbí ẹni tí ó ń gbani níyànjú, sí ìgbìyànjú; ẹni tí ń fi fún ni kí ó máa fi inú kan ṣe é; ẹni tí ń ṣe olórí, kí ó máa ṣe é ní ojú méjèèjì; ẹni tí ń sàánú, kí ó máa fi inú dídùn ṣe é.
9. Kí ìfẹ́ kí ó wà ní àìṣẹ̀tàn. Ẹ máa takéte sí ohun tí í ṣe búrubú; ẹ faramọ́ ohun tí í ṣe rere.
10. Níti ìfẹ́ ará, ẹ máa fi ìyọ́nú fẹ́ràn ara yín; níti ọlá, ẹ máa fi ẹnìkéjì yín ṣájú.
11. Níti iṣẹ́ ṣíṣe, ẹ má ṣe ọ̀lẹ; ẹ máa ní ìgbóná ọkàn; ẹ máa sìn Olúwa.
12. Ẹ máa yọ̀ ni ìrètí; ẹ máa mú sùúrù nínú ìpọ́njú; ẹ máa dúró gangan nínú àdúrà.
13. Ẹ máa pèsè fún àìní àwọn ènìyàn mímọ́; ẹ fi ara yín fún àlejò íṣe.
14. Ẹ máa súre fún àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí yín; ẹ máa súre, ẹ má sì ṣépè.
15. Àwọn tí ń yọ̀, ẹ má bá wọn yọ̀, àwọn tí ń sọkùn, ẹ má bá wọn sọkún.
16. Ẹ má wà ní inú kan náà sí ara yín. Ẹ má ṣe ronú ohun gíga, ṣùgbọ́n ẹ má tẹ̀lé onírẹ̀lẹ̀. Ẹ má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n ní ojú ara yín.
17. Ẹ má ṣe fi búburú san búburú fún ẹnikẹ́ni. Ẹ má pèsè ohun tí ó tọ́ níwájú gbogbo ènìyàn.
18. Bí ó le ṣe, bí ó ti wà ní ipa ti yín, ẹ má wà ní àlàáfíà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn.
19. Olùfẹ́, ẹ má ṣe gbẹ̀san ara yín, ṣùgbọ́n ẹ fi ààyè sílẹ̀ fún ìbínú; nítorí a ti kọ ọ́ pé, Olúwa wí pé, “Èmi ni ẹ̀san, èmi ó gbẹ̀san.”
20. Ṣùgbọ́n bí ebi bá ń pa ọ̀ta rẹ:“Fún un ní oúnjẹ; bí oùngbẹ bá ń gbẹ ẹ́,fún un ní omi mu;ní ṣíṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ ó kó ẹ̀yín iná lé e ní orí.”
21. Má ṣe jẹ́ kí búburú ṣẹ́gun rẹ, ṣùgbọ́n fi rere ṣẹ́gun búburú.