Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 6:8-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Ẹ má ṣe dà bí i wọn, nítorí Baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run mọ ohun tí ẹ ṣe aláìní, kí ẹ tilẹ̀ tó béèrè lọ́wọ́ rẹ̀.

9. “Nítorí náà, báyìí ni kí ẹ ṣe máa gbàdúrà:“ ‘Baba wa tí ń bẹ ní ọ̀run,ọ̀wọ̀ fún orukọ yín,

10. Kí ìjọba yín dé,Ìfẹ́ tiyín ni kí a ṣení ayé bí ti ọ̀run.

11. Ẹ fún wa ní oúnjẹ oòjọ́ wa lónìí

12. Ẹ dárí gbèsè wa jì wá,Bí àwa ti ń dárí ji àwọn ajigbésè wa,

13. Ẹ má ṣe fà wá sínú ìdẹwò,Ṣùgbọ́n ẹ gbà wá lọ́wọ́ ibi.Nítorí ìjọba ni tiyín, àti agbára àti ògo, láéláé, Àmín.’

14. Nítorí náà, bí ẹ̀yin bá dárí ji àwọn tó ṣẹ̀ yín, baba yín ọ̀run náà yóò dárí jì yín.

Ka pipe ipin Mátíù 6