Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 5:6-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Alábùkún fún ni àwọn tí ebi ń patí òùngbẹ ń gbẹ́ nítorí òdodo, nítorí wọn yóò yó.

7. Alábùkún-fún ni àwọn aláàánú,nítorí wọn yóò rí àánú gbà.

8. Alábùkún-fún ni àwọn ọlọ́kàn mímọ́,nítorí wọn yóò rí Ọlọ́run.

9. Alábùkún-fún ni àwọn tonílàjà,nítorí ọmọ Ọlọ́run ni a ó máa pè wọ́n.

10. Alábùkún-fún ni àwọn ẹni tí a ṣe inúnibíni sí,nítorí tí wọ́n jẹ́ olódodonítorí tiwọn ní ìjọba ọ̀run.

11. “Alábùkún-fún ni ẹ̀yin nígbà tí àwọn ènìyàn bá fi àbùkù kàn yín tí wọn bá ṣe inúnibíni sí yín, ti wọn fi ètè èké sọ̀rọ̀ búburú gbogbo sí yín nítorí mi.

12. Ẹ yọ̀, kí ẹ̀yin sì fò fún ayọ, nítorí ńlá ni èrè yín ní ọ̀run, nítorí bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ṣe inúnibíni sí àwọn wòlíì tí ń bẹ ṣáájú yín.

13. “Ẹ̀yin ni iyọ̀ ayé. Ṣùgbọ́n bí iyọ̀ bá di òbu kí ni a ó fi mú un dùn? Kò tún wúlò fún ohunkóhun mọ́, bí kò ṣe pé kí a dà á nù, kí ó sì di ohun tí ènìyàn ń fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.

14. “Ẹyin ni ìmọ́lẹ̀ ayé. Ìlú tí a tẹ̀dó sórí òkè kò lè fara sin.

Ka pipe ipin Mátíù 5