Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 26:62-67 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

62. Nígbà náà ni olórí àlùfáà sì dìde, ó wí fún Jésù pé, “Ẹ̀rí yìí ńkọ́? Ìwọ sọ bẹ́ẹ̀ tàbí ìwọ kò sọ bẹ́ẹ̀?”

63. Ṣùgbọ́n Jésù dákẹ́ rọ́rọ́.Nígbà náà ni olórí àlùfáà wí fún un pé, “Mo fi ọ́ bú ní orúkọ Ọlọ́run alààyè: Kí ó sọ fún wa, bí ìwọ bá í ṣe Kírísítì Ọmọ Ọlọ́run.”

64. Jésù sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, ìwọ wí,” Ṣùgbọ́n mo wí fún gbogbo yín. “Ẹ̀yin yóò rí Ọmọ-Ènìyàn ti yóò jókóó lọ́wọ́ ọ̀tún alágbára, tí yóò sì máa bọ̀ wá láti inú ìkùukù.”

65. Nígbà náà ni olórí àlùfáà fa aṣọ òun tikáraa rẹ̀ ya. Ó sì kígbe pé, “Ọ̀rọ̀ òdì! Kí ni a tún ń wá ẹlẹ́rìí fún? Gbogbo yín ti gbọ́ ọ̀rọ̀ òdì rẹ̀. Kí ni ìdájọ́ yín?”

66. Ki ni ẹ ti rò èyí sí.Gbogbo wọn sì kígbe lọ́hùn kan pé, “Ó jẹ̀bi ikú!”

67. Wọ́n tu itọ́ sí i ní ojú. Wọ́n gbá a lẹ́sẹ̀ẹ́. Àwọn ẹlòmíràn sì gbá a lójú.

Ka pipe ipin Mátíù 26